Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Verset: (45) Sourate: AZ-ZOUKHROUF
وَسۡـَٔلۡ مَنۡ أَرۡسَلۡنَا مِن قَبۡلِكَ مِن رُّسُلِنَآ أَجَعَلۡنَا مِن دُونِ ٱلرَّحۡمَٰنِ ءَالِهَةٗ يُعۡبَدُونَ
Bèèrè wò lọ́wọ́ àwọn tí A rán níṣẹ́ ṣíwájú rẹ nínú àwọn Òjíṣẹ́ Wa (pé): “Ǹjẹ́ A sọ àwọn kan di ọlọ́hun tí wọn yóò máa jọ́sìn fún lẹ́yìn Àjọkẹ́-ayé bí?”¹
1. “Bèèrè wò lọ́wọ́ àwọn tí A rán níṣẹ́ ṣíwájú rẹ nínú àwọn Òjíṣẹ́ Wa”. Àgbọ́yé méjì ni àwọn tafsīr mú wá lórí rẹ̀.
Àgbọ́yé kìíní ni pé, ìbéèrè náà wáyé nínú ìrìn-àjò òru àti ìgun-sánmọ̀ tí Allāhu mú Ànábì wa - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - rìn.
Àgbọ́yé kejì ni pé, ìbéèrè náà wáyé láààrin Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - àti àwọn tó nímọ̀ nípa Taorāt àti ’Injīl. Ìyẹn ni pé, kí ni àwọn tírà méjèèjì sọ nípa “ta ni a gbọ́dọ̀ máa jọ́sìn fún ní ọ̀nà òdodo, ṣé Allāhu ni tàbí àwọn ọlọ́hun mìíràn?”
Nípa àgbọ́yé kejì yìí, dídárúkọ àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu nínú āyah yìí dípò àwọn tírà wọn jọ bí Allāhu ṣe pàṣẹ pé “Tí ẹ bá yapa-ẹnu lórí kiní kan, ẹ ṣẹ́rí rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ Allāhu àti ọ̀dọ̀ Òjíṣẹ́ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - (ìyẹn nínú sūrah an-Nisā’; 4:59), tí èyí sì túmọ̀ sí al-Ƙur’ān àti sunnah Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -.
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Verset: (45) Sourate: AZ-ZOUKHROUF
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture