クルアーンの対訳 - ヨルバ語対訳 * - 対訳の目次

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

対訳 節: (50) 章: 部族連合章
يَٰٓأَيُّهَا ٱلنَّبِيُّ إِنَّآ أَحۡلَلۡنَا لَكَ أَزۡوَٰجَكَ ٱلَّٰتِيٓ ءَاتَيۡتَ أُجُورَهُنَّ وَمَا مَلَكَتۡ يَمِينُكَ مِمَّآ أَفَآءَ ٱللَّهُ عَلَيۡكَ وَبَنَاتِ عَمِّكَ وَبَنَاتِ عَمَّٰتِكَ وَبَنَاتِ خَالِكَ وَبَنَاتِ خَٰلَٰتِكَ ٱلَّٰتِي هَاجَرۡنَ مَعَكَ وَٱمۡرَأَةٗ مُّؤۡمِنَةً إِن وَهَبَتۡ نَفۡسَهَا لِلنَّبِيِّ إِنۡ أَرَادَ ٱلنَّبِيُّ أَن يَسۡتَنكِحَهَا خَالِصَةٗ لَّكَ مِن دُونِ ٱلۡمُؤۡمِنِينَۗ قَدۡ عَلِمۡنَا مَا فَرَضۡنَا عَلَيۡهِمۡ فِيٓ أَزۡوَٰجِهِمۡ وَمَا مَلَكَتۡ أَيۡمَٰنُهُمۡ لِكَيۡلَا يَكُونَ عَلَيۡكَ حَرَجٞۗ وَكَانَ ٱللَّهُ غَفُورٗا رَّحِيمٗا
Ìwọ Ànábì, dájúdájú Àwa ṣe é ní ẹ̀tọ́ fún ọ àwọn ìyàwó rẹ̀, tí o fún ní owó-orí wọn, àti àwọn ẹrú rẹ nínú àwọn tí Allāhu fí ṣe ìkógun fún ọ àti àwọn ọmọbìnrin arákùnrin bàbá rẹ àti àwọn ọmọbìnrin arábìnrin bàbá rẹ, àti àwọn ọmọbìnrin arákùnrin ìyá rẹ, àti àwọn ọmọbìnrin arábìnrin ìyá rẹ, àwọn tó fi ìlú Mọkkah sílẹ̀ wá sí ìlú Mọdīnah pẹ̀lú rẹ, àti onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, tí ó bá fi ara rẹ̀ tọrẹ fún Ànábì, tí Ànábì náà sì fẹ́ fi ṣe ìyàwó. Ìwọ nìkan ni (èyí) wà fún, kò sí fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin. A ti mọ ohun tí A ṣe ní ẹ̀tọ́ fún wọn nípa àwọn ìyàwó wọn àti àwọn ẹrú wọn.¹ (Èyí rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí ó má baà sí láìfí fún ọ. Allāhu sì ń jẹ́ Aláforíjìn, Àṣàkẹ́-ọ̀run.
1. Ohun tí Allāhu ṣe ní ẹ̀tọ́ fún àwa nípa ìgbéyàwó àwa ọmọlẹ́yìn Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - :
ìkíní: Fífẹ́ onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin pẹ̀lú àṣẹ àti ìyọ̀ǹda aláṣẹ rẹ̀. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah an-Nisā’; 4:25.
Ìkejì: Fífẹ́ obìnrin pẹ̀lú sọ̀daàkí. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah an-Nisā’; 4:4.
Ìkẹta: Òǹkà ìyàwó mùsùlùmí kò gbọdọ̀ tayọ mẹ́rin ní abẹ́ àkóṣo rẹ̀. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah an-Nisā’; 4:3.
アラビア語 クルアーン注釈:
 
対訳 節: (50) 章: 部族連合章
章名の目次 ページ番号
 
クルアーンの対訳 - ヨルバ語対訳 - 対訳の目次

クルアーン・ヨルバ語対訳 - Abu Rahima Mikhail Aikweiny ヒジュラ暦1432年印刷

閉じる