Àwọn ọkùnrin ní ìpín nínú ohun tí òbí méjèèjì àti ẹbí fi sílẹ̀. Àti pé àwọn obìnrin náà ní ìpín nínú ohun tí òbí méjéèjì àti ẹbí fi sílẹ̀. Nínú ohun tó kéré nínú rẹ̀ tàbí tó pọ̀; (ó jẹ́) ìpín tí wọ́n ti pín (tí wọ́n ti ṣàdáyanrí rẹ̀ fún wọn).
Tiyín ni ìlàjì ohun tí àwọn ìyàwó yín fi sílẹ̀, tí wọn kò bá ní ọmọ. Tí wọ́n bá sì ní ọmọ, tiyín ni ìdá kan nínú ìdá mẹ́rin ohun tí wọ́n fi sílẹ̀, lẹ́yìn àsọọ́lẹ̀ tí wọ́n sọ tàbí gbèsè. Tiwọn sì ni ìdá kan nínú ìdá mẹ́rin ohun tí ẹ fi sílẹ̀, tí ẹ̀yin kò bá ní ọmọ láyé. Tí ẹ bá ní ọmọ láyé, ìdá kan nínú ìdá mẹ́jọ ni tiwọn nínú ohun tí ẹ fi sílẹ̀ lẹ́yìn àsọọ́lẹ̀ tí ẹ sọ tàbí gbèsè. Tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan tí wọ́n fẹ́ jogún rẹ̀ kò bá ní òbí àti ọmọ, tí ó sì ní arákùnrin kan tàbí arábìnrin kan, ìdá kan nínú ìdá mẹ́fà ni ti ìkọ̀ọ̀kan àwọn méjèèjì. Tí wọ́n bá sì pọ̀ ju bẹ́ẹ̀ lọ, wọn yóò dìjọ pín ìdá kan nínú ìdá mẹ́ta, lẹ́yìn àsọọ́lẹ̀ tí wọ́n sọ tàbí gbèsè, tí kò níí jẹ́ ìpalára. Àsọọ́lẹ̀ (òfin) kan ni láti ọ̀dọ̀ Allāhu. Allāhu sì ni Onímọ̀, Aláfaradà.
Àwọn méjì tí wọ́n ṣe sìná nínú yín, kí ẹ (fi ẹnu tàbí ọwọ́) bá wọn wí.¹ Tí wọ́n bá sì ronú pìwàdà, tí wọ́n ṣàtúnṣe, kí ẹ mójú kúrò lára wọn. Dájúdájú Allāhu ń jẹ́ Olùgba-ìronúpìwàdà, Àṣàkẹ́- ọ̀run.
1. Wọ́n ti fi sūrah an-Nūr; 24:2 pa ìdájọ́ āyah yìí rẹ̀ nítorí pé, āyah méjèèjì dálé ìjìyà fún onísìná tí kò ì ṣe ìgbéyàwó rí.
Ẹ̀yin tí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo, ẹ má ṣe fi èrú jẹ dúkìá yín láààrin ara yín àyàfi kí ó jẹ́ òwò ṣíṣe pẹ̀lú ìyọ́nú láààrin ara yín. Ẹ má ṣe para yín. Dájúdájú Allāhu ń jẹ́ Aláàánú si yín.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ṣe ìyẹn láti fi tayọ ẹnu-ààlà àti láti fi ṣe àbòsí, láìpẹ́ A máa mú un wọ inú Iná. Ìrọ̀rùn sì ni ìyẹn jẹ́ fún Allāhu.
Ìkọ̀ọ̀kan (àwọn dúkìá) ni A ti ṣe àdáyanrí rẹ̀ fún àwọn tí ó máa jogún rẹ̀ nínú ohun tí àwọn òbí àti ẹbí fi sílẹ̀. Àwọn tí ẹ sì búra fún (pé ẹ máa fún ní n̄ǹkan), ẹ fún wọn ní ìpín wọn. Dájúdájú Allāhu ń jẹ́ Ẹlẹ́rìí lórí gbogbo n̄ǹkan.
Àwọn tó ń ṣahun, (àwọn) tó ń pa ènìyàn láṣẹ ahun ṣíṣe àti (àwọn) tó ń fi ohun tí Allāhu fún wọn nínú oore àjùlọ Rẹ̀ pamọ́; A ti pèsè ìyà tí í yẹpẹrẹ ẹ̀dá sílẹ̀ de àwọn aláìgbàgbọ́.
Kí ni ìpalára tí ó máa ṣe fún wọn tí wọ́n bá gbàgbọ́ nínú Allāhu àti Ọjọ́ Ìkẹ́yìn, tí wọ́n sì ná nínú ohun tí Allāhu ṣe ní arísìkí fún wọn? Allāhu sì jẹ́ Onímọ̀ nípa wọ́n.
Ní ọjọ́ yẹn, àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, tí wọ́n sì yapa Òjíṣẹ́ náà, wọ́n á fẹ́ kí àwọn bá ilẹ̀ dọ́gba (kí wọ́n di erùpẹ̀). Wọn kò sì lè fi ọ̀rọ̀ kan pamọ́ fún Allāhu.
Tàbí wọ́n ń ṣe ìlara àwọn ènìyàn lórí ohun tí Allāhu fún wọn nínú oore àjùlọ Rẹ̀ ni? Dájúdájú A fún àwọn ẹbí (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm ní Tírà àti òye ìjìnlẹ̀ (sunnah). A sì fún wọn ní ìjọba ńlá.
Àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, A óò mú wọn wọ inú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Olùṣegbére ni wọ́n nínú rẹ̀ títí láéláé. Àwọn ìyàwó mímọ́ ń bẹ fún wọn nínú rẹ̀. A sì máa fi wọ́n sí abẹ́ ibòji tó máa ṣíji bò wọ́n dáradára.
Ṣé ìwọ kò wòye sí àwọn tó ń sọ̀rọ̀ (tí kò sì rí bẹ́ẹ̀) pé dájúdájú àwọn gbàgbọ́ nínú ohun tí A sọ̀kalẹ̀ fún ọ àti ohun tí A sọ̀kalẹ̀ ṣíwájú rẹ, tí wọ́n sì ń gbèrò láti gbé ẹjọ́ lọ bá òrìṣà, A sì ti pa wọ́n láṣẹ pé kí wọ́n lòdì sí i. Èṣù sì fẹ́ ṣì wọ́n lọ́nà ní ìṣìnà tó jìnnà.
Báwo ni ó ṣe jẹ́ pé nígbà tí àdánwò kan bá kàn wọ́n nípasẹ̀ ohun tí ọwọ́ wọ́n tì síwájú, lẹ́yìn náà wọ́n máa wá bá ọ, wọ́n yó sì máa fi Allāhu búra pé kò sí ohun tí a gbàlérò bí kò ṣe dáadáa àti ìrẹ́pọ̀.
A kò rán Òjíṣẹ́ kan níṣẹ́ àfi nítorí kí wọ́n lè tẹ̀lé e pẹ̀lú ìyọ̀ǹda Allāhu. Tí ó bá jẹ́ pé nígbà tí wọ́n ṣàbòsí sí ẹ̀mí ara wọn, wọ́n wá bá ọ,¹ wọ́n sì tọrọ àforíjìn Allāhu, tí Òjíṣẹ́ sì tún bá wọn tọrọ àforíjìn, wọn ìbá kúkú rí Allāhu ní Olùgba-ìronúpìwàdà, Àṣàkẹ́-ọ̀run.
1. Ìyẹn nígbà tí Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -wà nílé ayé ṣíwájú kí ó tó kú. Àmọ́ lẹ́yìn ikú rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - kò sí àǹfààní fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti lọ bá a nídìí sàréè rẹ̀. Tí ènìyàn kan bá dán an wò pẹ́rẹ́, ó máa kó sínú ẹbọ ńlá. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah āli-’Imrọ̄n; 3:101.
Tí ó bá jẹ́ pé A ṣe é ní ọ̀ran- anyàn fún wọn pé: "Ẹ pa ara yín tàbí ẹ jáde kúrò nínú ìlú yín," wọn kò níí ṣe é àfi díẹ̀ nínú wọn. Tí ó bá tún jẹ́ pé wọ́n ṣe ohun tí A fi ń ṣe wáàsí fún wọn ni, ìbá jẹ́ oore àti ìdúróṣinṣin tó lágbára jùlọ fún wọn.
86. Nígbà tí wọ́n bá ki yín ní kíkí kan, ẹ kí wọn (padà) pẹ̀lú èyí tó dára jù ú lọ tàbí kí ẹ dá a padà (pẹ̀lú bí wọ́n ṣe ki yín). Dájúdájú Allāhu ń jẹ́ Olùṣírò lórí gbogbo n̄ǹkan.
Dájúdájú àwọn tí mọlāika gba ẹ̀mí wọn, (lásìkò) tí wọ́n ń ṣàbòsí sí ẹ̀mí ara wọn, (àwọn mọlāika) sọ pé: “Kí ni ẹ̀ ń ṣe (nínú ẹ̀sìn)?¹” Wọ́n wí pé: “Wọ́n dá wa lágara lórí ilẹ̀ ni.” (Àwọn mọlāika) sọ pé: “Ṣé ilẹ̀ Allāhu kò fẹ̀ tó (fún yín) láti gbé ẹ̀sìn yín sá lórí ilẹ̀?” Àwọn wọ̀nyẹn, iná Jahanamọ ni ibùgbé wọn. Ó sì burú ní ìkángun.
1. Tàbí “nínú igun wo ni ẹ wà, igun àwọn mùsùlùmí ni tàbí igun àwọn ọ̀ṣẹbọ? Tàbí nínú ìlú wo ni ẹ wà, ìlú 'Islām ni tàbí ìlú ọ̀ṣẹbọ? ”
Wọ́n ń fi ara pamọ́ fún àwọn ènìyàn, wọn kò sì lè fara pamọ́ fún Allāhu (nítorí pé) Ó wà pẹ̀lú wọn (pẹ̀lú ìmọ̀ Rẹ̀) nígbà tí wọ́n ń pètepèrò lórí ohun tí (Allāhu) kò yọ́nú sí nínú ọ̀rọ̀ sísọ.¹ Allāhu sì ń jẹ́ Alámọ̀tán nípa ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
Kíyè sí i, ẹ̀yin wọ̀nyí ni ẹ̀ ń bá wọn mú àwíjàre wá nílé ayé. Ta ni ó máa bá wọn mú àwíjàre wá ní ọ̀dọ̀ Allāhu ní Ọjọ́ Àjíǹde? Tàbí ta ni ó máa jẹ́ aláàbò fún wọn?
Dájúdájú mo máa ṣì wọ́n lọ́nà. Dájúdájú mo máa tàn wọ́n jẹ. Dájúdájú mo máa pa wọ́n láṣẹ, wọn yó sì máa gé etí ẹran-ọ̀sìn (láti yà á sọ́tọ̀ fún òrìṣà). Dájúdájú mo máa pa wọ́n láṣẹ, wọn yó sì máa yí ẹ̀sìn Allāhu padà.”¹ Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú Èṣù ní ọ̀rẹ́ lẹ́yìn Allāhu, dájúdájú ó ti ṣòfò ní òfò pọ́nńbélé.
1. Ìyẹn ni pé, Èṣù yóò máa pa wọ́n ní àṣẹ pé kí wọ́n di kèfèrí àti ọ̀ṣẹbọ. Allāhu sì ń pàṣẹ pé wọn kò gbọ́dọ̀ yí ẹ̀sìn wọn tí ó jẹ́ ẹ̀sìn àdámọ́ wọn padà. Ẹ wo sūrah ar-Rūm; 30:30.
Àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣiṣẹ́ rere, A máa mú wọn wọ inu àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Olùṣegbére ni wọn nínú rẹ̀ títí láéláé. (Ó jẹ́) àdéhùn Allāhu ní ti òdodo. Ta sì ni ó sọ òdodo ju Allāhu?
Wọ́n ń ṣe bàlàbàlà síhìn-ín sọ́hùn-ún, wọn kò jẹ́ ti àwọn wọ̀nyí, wọn kò sì jẹ́ ti àwọn wọ̀nyí. Ẹnikẹ́ni tí Allāhu bá ṣì lọ́nà, o ò sì níí rí ọ̀nà kan fún un.
A gbé àpáta sókè orí wọn nítorí májẹ̀mu wọn. A sì sọ fún wọn pé: “Ẹ gba ẹnu-ọ̀nà ìlú wọlé ní olùdáwọ́tẹ-orúnkún.” A tún sọ fún wọn pé: “Ẹ má ṣe tayọ ẹnu-ààlà ní ọjọ́ Sabt.” A sì gba àdéhùn tó nípọn lọ́wọ́ wọn.
Nítorí yíyẹ̀ tí wọ́n fúnra wọn yẹ àdéhùn wọn, àti ṣíṣàìgbàgbọ́ wọn nínú àwọn ọ̀rọ̀ Allāhu, àti pípa tí wọ́n ń pa àwọn Ànábì láì lẹ́tọ̀ọ́ àti wíwí tí wọ́n ń wí pé: “Ọkàn wa ti di.” - rárá, Allāhu ti fi èdídí dí ọkàn wọn ni nítorí àìgbàgbọ́ wọn. - Nítorí náà, wọn kò níí gbàgbọ́ àfi díẹ̀ (nínú wọn).
Àti nítorí ọ̀rọ̀ wọn (yìí): “Dájúdájú àwa pa Mọsīh ‘Īsā ọmọ Mọryam Òjíṣẹ́ Allāhu.” Wọn kò pa á, wọn kò sì kàn án mọ́ igi àgbélébùú, ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni.¹ Dájúdájú àwọn tó yapa-ẹnu lórí rẹ̀, kúkú wà nínú iyèméjì lórí rẹ̀; kò sí ìmọ̀ kan fún wọn nípa rẹ̀ àfi títẹ̀lé àbá dídá. Wọn kò pa á ní ti àmọ̀dájú.
1. Kíyè sí ìyàtọ̀ pàtàkì tó wà láààrin awẹ́ gbólóhùn méjì yìí:
Ìkíní “ وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْۚ” ìtúmọ̀ rẹ̀ ni “وَلَكِنْ أُلْقِيَ شَبَهُهُ عَلَى غَيْرِهِ لهم” “ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni.” Ìyẹn ni pé, àwọn ọ̀tá Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a -, wọ́n kan ẹnì kan mọ́ igi àgbélébùú, wọ́n sì pa onítọ̀ún sórí igi àgbélébùú nítorí pé, Allāhu ti gbé àwòrán àti ìrísí Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - wọ ẹni tí ó gba ikú Ànábì ‘Īsā kú. Onítọ̀ún gan-an ni wọ́n kàn mọ́ igi àgbélébùú, kì í ṣe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a -. Èyí sì ni ète ti Allāhu tí Ó fi gba Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìdí sì nìyí tí àwọn ọ̀tá rẹ̀ fi wà nínú iyèméjì nípa ta gan-an ni wọ́n kàn mọ́ igi àgbélébùú nítorí pé, ìrísí àwọn méjèèjì ló jọra wọn, ohùn àwọn méjèèjì kò jọra wọn rárá.
Síwájú sí i, ẹ̀kọ́ nípa mọfọ́lọ́jì èdè Lárúbáwá (ìyẹn ‘ilmu-ssọrf) fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ọ̀rọ̀-orúkọ fún “شُبِّهَ” tó jẹyọ pẹ̀lú háràfí “lām” nínú awẹ́ gbólóhùn “ وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْۚ” jẹ́ “شَبَهٌ” (ṣabahun / ṣabah) tàbí “شِبْهٌ” (ṣibhun / ṣibh) - ìtúmọ̀ “ìjọra / àfijọ. Àti pé àkòónú “شَبَهٌ”/ “شِبْهٌ” (ṣabahun / ṣibhun) nígbà náà ni pé, wọ́n ń lò ó fún n̄ǹkan méjì tó jẹ́ oríṣìí méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àmọ́ tí wọ́n jọra wọn ní àwòrán. Ìtúmọ̀ yìí sì ni gbogbo ọ̀rọ̀ tó pilẹ̀ lórí àwọn háràfí mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí “ش ب ه” ní nínú al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé. Ẹ wo àwọn àyè náà; sūrah al-Baƙọrah; 2:25, sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:7, sūrah al-’Ani‘ām; 6: 99 àti 141, àti sūrah as-Zumọr; 39:23.
Ìkejì, “وَلَكِنْ شُبِّهَ عَلَيْهِمْ” ìtúmọ̀ rẹ̀ ni “وَلَكِنِ اشْتُبِهَ عَلَيْهِمْ ” “ṣùgbọ́n a fi rú wọn lójú / ṣùgbọ́n a dà á rú mọ́ wọn lójú”. Ìyẹn sì kọ́ ni al-Ƙur’ān sọ. Wòóore, ẹ̀kọ́ nípa mọfọ́lọ́jì èdè Lárúbáwá (‘ilmu-ssọrf) tún fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ọ̀rọ̀-orúkọ fún “شُبِّهَ” tó jẹyọ pẹ̀lú háràfí “ ‘alā” nínú gbólóhùn yìí jẹ́ “شُبْهَةٌ” (ṣubhatun / ṣubhah) – ìtúmọ̀: “ìrújú / rújúrújú”. Àmọ́ sá, “ìjọra” máa ń yọrí sí “ìrújú” nígbà tí kò bá sí “àmọ̀dájú”.
Àkíyèsí kejì: Gbogbo tírà tafsīr tó sọ̀rọ̀ lórí “وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْ” “ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni.” l’ó mú ọ̀rọ̀ wá lórí bí Allāhu - subhānahu wa ta‘ālā - ṣe gbé àwòrán ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - wọ ẹnì kan nínú àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀. Kódà wọ́n gba ọ̀rọ̀ náà wá ni láti ọ̀dọ̀ Ọmọ ‘Abbās - kí Allāhu yọ́nú sí àwọn méjèèjì -, gẹ́gẹ́ bí a ṣe lè rí i kà nínú tafsīr Zādu-l-Mọsīr. Ẹni tí kò bá ní ìmọ̀ nípa ipò Ọmọ ‘Abbās - kí Allāhu yọ́nú sí àwọn méjèèjì - nínú ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ al-Ƙur’ān tàbí ẹni tí kò bá ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ hadīth l’ó lè pe ìtàn náà ní ìtàn ’Isrọ̄’īliyāt
bí kò ṣe pé Allāhu gbé e wá sókè lọ́dọ̀ Rẹ̀ ni. Allāhu sì ń jẹ́ Alágbára, Ọlọ́gbọ́n.¹
1. Āyah 157 àti 158 yìí jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn āyah tí ó sọ ìjọ Ahmadiyyah Ƙọ̄diyaniyyah tàbí Lahọ̄riyyah) di ìjọ kèfèrí. Ìdí ni pé, ìgbàgbọ́ ìjọ Ahmadiyyah ni pé, wọn kan ‘Īsā ọmọ Mọryam mọ́ igi àgbélébùú - kí ọlà Allāhu máa bá a -, àmọ́ kò kú sí orí rẹ̀. Ìjọ Ahmadiyyah sì tún gbà pé ‘Īsā ọmọ Mọryam sá àsálà wá sí ilẹ̀ India. Ó fẹ́ ìyàwó níbẹ̀. Ó kú síbẹ̀. Wọ́n sì sin ín síbẹ̀. Lẹ́yìn náà, ìjọ Ahmadiyyah gbà pé ẹni tí ó padà wá sáyé lábẹ́ ìpadàbọ̀ ‘Īsā ọmọ Mọryam kò jẹ́ ẹnì kan bí kò ṣe mirza Ghulam Ahmad, olùdásílẹ̀ ìjọ Ahmadiyyah.
Ọ̀nà tí èyí sì gbà ṣẹlẹ̀ nìyí nínú ìtọ́kasí wọn: “The word of God which I set out at some places in my book, the Baraheen Ahmadiyya explains how God Almighty made me Isa Son of Mary. In that book God first named me Mary and then disclosed that God had breathed His spirit into this Mary and said that after the breathing of this spirit my status as Mary was converted into my status as Isa, and thus Isa having been born of Mary was called Son of Mary.” Ìtúmọ̀: Mirza Ghulam Ahmad wí pé “Ọ̀rọ̀ Allāhu tí mo mú jáde láti inú ìwé mi, Baraheen Ahmadiyya, ó ń ṣe àlàyé ọ̀nà tí Allāhu gbà sọ mí di ‘Īsā ọmọ Mọryam. Nínú ìwé yẹn, Allāhu kọ́ sọ mí ní Mọryam. Lẹ́yìn náà, wọ́n fi hàn mí pé Allāhu ti fẹ́ ẹ̀mí mímọ́ Rẹ̀ sí Mọryam yìí lára. Ó sì sọ pé lẹ́yìn tí Òun ti fẹ́ ẹ̀mí mímọ́ sí mi lára, ipò mi gẹ́gẹ́ bí Mọryam ti paradà báyìí, mo sì ti di ‘Īsā. Èyí rí bẹ́ẹ̀ fún wí pé bíbí tí Mọryam bí ‘Īsā ni wọ́n fi ń pè é ní ‘Īsā ọmọ Mọryam. [Ìwé Tadhkirah, òǹkọ̀wé: = = (Ahmadi) Muhammad Zafrullah Khan; ojú ewé: 369.] Ibi dandan Allāhu kí ó máa bá òpùrọ́ yìí.
Nítorí àbòsí láti ọ̀dọ̀ àwọn tí wọ́n di yẹhudi, A ṣe àwọn n̄ǹkan dáadáa kan ní èèwọ̀ fún wọn, èyí tí wọ́n ṣe ní ẹ̀tọ́ fún wọn (tẹ́lẹ̀. A ṣe é ní èèwọ̀ fún wọn sẹ́) nípa bí wọ́n ṣe ń ṣẹ́rí ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ kúrò lójú ọ̀nà (ẹ̀sìn) Allāhu.
Àti gbígbà tí wọ́n ń gba owó èlé, tí A sì ti kọ̀ ọ́ fún wọn, àti jíjẹ tí wọ́n ń jẹ dúkìá àwọn ènìyàn lọ́nà èrú. A sì ti pèsè ìyà ẹlẹ́ta-eléro sílẹ̀ de àwọn aláìgbàgbọ́.
Àti àwọn Òjíṣẹ́ kan tí A ti sọ ìtàn wọn fún ọ ṣíwájú pẹ̀lú àwọn Òjíṣẹ́ kan tí A kò sọ ìtàn wọn fún ọ. Allāhu sì bá (Ànábì) Mūsā sọ̀rọ̀ tààrà.
Contents of the translations can be downloaded and re-published, with the following terms and conditions:
1. No modification, addition, or deletion of the content.
2. Clearly referring to the publisher and the source (QuranEnc.com).
3. Mentioning the version number when re-publishing the translation.
4. Keeping the transcript information inside the document.
5. Notifying the source (QuranEnc.com) of any note on the translation.
6. Updating the translation according to the latest version issued from the source (QuranEnc.com).
7. Inappropriate advertisements must not be included when displaying translations of the meanings of the Noble Quran.
ئەنجامەکانی گەڕان:
API specs
Endpoints:
Sura translation
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/sura/{translation_key}/{sura_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified sura (by its number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114)
Returns:
json object containing array of objects, each object contains the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/aya/{translation_key}/{sura_number}/{aya_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified aya (by its number sura_number and aya_number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114) aya_number: [1-...] (Aya number in the sura)
Returns:
json object containing the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".