വിശുദ്ധ ഖുർആൻ പരിഭാഷ - യോറുബൻ വിവർത്തനം * - വിവർത്തനങ്ങളുടെ സൂചിക

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

പരിഭാഷ അദ്ധ്യായം: സൂറത്തുൽ ഖിയാമഃ   ആയത്ത്:

Suuratul-Qiyaamah

لَآ أُقۡسِمُ بِيَوۡمِ ٱلۡقِيَٰمَةِ
Èmi (Allāhu) ń fi Ọjọ́ Àjíǹde búra.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَلَآ أُقۡسِمُ بِٱلنَّفۡسِ ٱللَّوَّامَةِ
Mo tún ń fi ẹ̀mí tó máa dá ara rẹ̀ ní ẹ̀bi búra.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَلَّن نَّجۡمَعَ عِظَامَهُۥ
Ṣé ènìyàn lérò pé A kò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
بَلَىٰ قَٰدِرِينَ عَلَىٰٓ أَن نُّسَوِّيَ بَنَانَهُۥ
Rárá. (À ń jẹ́) Alágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.
1.Àwọn ọmọníka ọwọ́ àti ọmọníka ẹsẹ̀, ọ̀tún rẹ̀ àti òsì rẹ̀. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Mọ̄‘rij; 70:40-41.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
بَلۡ يُرِيدُ ٱلۡإِنسَٰنُ لِيَفۡجُرَ أَمَامَهُۥ
Rárá ènìyàn fẹ́ máa ṣe aburú lọ bẹ́ẹ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
يَسۡـَٔلُ أَيَّانَ يَوۡمُ ٱلۡقِيَٰمَةِ
ni ó fi ń bèèrè pé: “Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?”
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
فَإِذَا بَرِقَ ٱلۡبَصَرُ
Nígbà tí ojú bá rí ìdààmú tó sì yà sílẹ̀ tí kò lè padé,
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَخَسَفَ ٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَجُمِعَ ٱلشَّمۡسُ وَٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí wọ́n bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn tí ìmọ́lẹ̀ méjèèjì pòóró,
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
يَقُولُ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذٍ أَيۡنَ ٱلۡمَفَرُّ
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: “Níbo ni ibùsásí wà?”
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
كَلَّا لَا وَزَرَ
Rárá, kò sí ibùsásí.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمُسۡتَقَرُّ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
يُنَبَّؤُاْ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذِۭ بِمَا قَدَّمَ وَأَخَّرَ
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun tó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
بَلِ ٱلۡإِنسَٰنُ عَلَىٰ نَفۡسِهِۦ بَصِيرَةٞ
Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَلَوۡ أَلۡقَىٰ مَعَاذِيرَهُۥ
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
لَا تُحَرِّكۡ بِهِۦ لِسَانَكَ لِتَعۡجَلَ بِهِۦٓ
Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
إِنَّ عَلَيۡنَا جَمۡعَهُۥ وَقُرۡءَانَهُۥ
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
فَإِذَا قَرَأۡنَٰهُ فَٱتَّبِعۡ قُرۡءَانَهُۥ
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
ثُمَّ إِنَّ عَلَيۡنَا بَيَانَهُۥ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
كَلَّا بَلۡ تُحِبُّونَ ٱلۡعَاجِلَةَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé ni.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَتَذَرُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Ẹ sì ń gbé ọ̀run jù sílẹ̀.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ نَّاضِرَةٌ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
إِلَىٰ رَبِّهَا نَاظِرَةٞ
Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَوُجُوهٞ يَوۡمَئِذِۭ بَاسِرَةٞ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
تَظُنُّ أَن يُفۡعَلَ بِهَا فَاقِرَةٞ
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé wọ́n máa fi aburú kan òhun.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
كَلَّآ إِذَا بَلَغَتِ ٱلتَّرَاقِيَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَقِيلَ مَنۡۜ رَاقٖ
A sì máa sọ pé: “Ǹjẹ́ olùpọfọ̀ kan wà bí (tí ó máa pọfọ̀ láti gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَظَنَّ أَنَّهُ ٱلۡفِرَاقُ
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَٱلۡتَفَّتِ ٱلسَّاقُ بِٱلسَّاقِ
Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمَسَاقُ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
فَلَا صَدَّقَ وَلَا صَلَّىٰ
Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
وَلَٰكِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰ
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo ní irọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
ثُمَّ ذَهَبَ إِلَىٰٓ أَهۡلِهِۦ يَتَمَطَّىٰٓ
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰ
(Ìparun nílé ayé) ló tọ́ sí ọ jùlọ (lórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ wọ̀nyẹn). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
ثُمَّ أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰٓ
Lẹ́yìn náà, (Iná) ló tọ́ sí ọ jùlọ (ní ọ̀run). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَن يُتۡرَكَ سُدًى
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
أَلَمۡ يَكُ نُطۡفَةٗ مِّن مَّنِيّٖ يُمۡنَىٰ
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
ثُمَّ كَانَ عَلَقَةٗ فَخَلَقَ فَسَوَّىٰ
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é tó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
فَجَعَلَ مِنۡهُ ٱلزَّوۡجَيۡنِ ٱلذَّكَرَ وَٱلۡأُنثَىٰٓ
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti ara rẹ̀, akọ àti abo.
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
أَلَيۡسَ ذَٰلِكَ بِقَٰدِرٍ عَلَىٰٓ أَن يُحۡـِۧيَ ٱلۡمَوۡتَىٰ
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
അറബി ഖുർആൻ വിവരണങ്ങൾ:
 
പരിഭാഷ അദ്ധ്യായം: സൂറത്തുൽ ഖിയാമഃ
സൂറത്തുകളുടെ സൂചിക പേജ് നമ്പർ
 
വിശുദ്ധ ഖുർആൻ പരിഭാഷ - യോറുബൻ വിവർത്തനം - വിവർത്തനങ്ങളുടെ സൂചിക

വിശുദ്ധ ഖുർആൻ ആശയവിവർത്തനം (യോറുബൻ ഭാഷയിൽ). ശൈഖ് അബൂ റഹീമഃ മീകാഈൽ അയ്കൂബീനീ നടത്തിയ വിവർത്തനം. ഹി 1432 ലെ പതിപ്പ്.

അടക്കുക