Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Surah: Al-Qiyāmah   Ayah:

Suuratul-Qiyaamah

لَآ أُقۡسِمُ بِيَوۡمِ ٱلۡقِيَٰمَةِ
Èmi (Allāhu) ń fi Ọjọ́ Àjíǹde búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَآ أُقۡسِمُ بِٱلنَّفۡسِ ٱللَّوَّامَةِ
Mo tún ń fi ẹ̀mí tó máa dá ara rẹ̀ ní ẹ̀bi búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَلَّن نَّجۡمَعَ عِظَامَهُۥ
Ṣé ènìyàn lérò pé A kò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
Arabic explanations of the Qur’an:
بَلَىٰ قَٰدِرِينَ عَلَىٰٓ أَن نُّسَوِّيَ بَنَانَهُۥ
Rárá. (À ń jẹ́) Alágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.
1.Àwọn ọmọníka ọwọ́ àti ọmọníka ẹsẹ̀, ọ̀tún rẹ̀ àti òsì rẹ̀. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Mọ̄‘rij; 70:40-41.
Arabic explanations of the Qur’an:
بَلۡ يُرِيدُ ٱلۡإِنسَٰنُ لِيَفۡجُرَ أَمَامَهُۥ
Rárá ènìyàn fẹ́ máa ṣe aburú lọ bẹ́ẹ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀
Arabic explanations of the Qur’an:
يَسۡـَٔلُ أَيَّانَ يَوۡمُ ٱلۡقِيَٰمَةِ
ni ó fi ń bèèrè pé: “Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?”
Arabic explanations of the Qur’an:
فَإِذَا بَرِقَ ٱلۡبَصَرُ
Nígbà tí ojú bá rí ìdààmú tó sì yà sílẹ̀ tí kò lè padé,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَخَسَفَ ٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَجُمِعَ ٱلشَّمۡسُ وَٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí wọ́n bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn tí ìmọ́lẹ̀ méjèèjì pòóró,
Arabic explanations of the Qur’an:
يَقُولُ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذٍ أَيۡنَ ٱلۡمَفَرُّ
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: “Níbo ni ibùsásí wà?”
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّا لَا وَزَرَ
Rárá, kò sí ibùsásí.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمُسۡتَقَرُّ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
Arabic explanations of the Qur’an:
يُنَبَّؤُاْ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذِۭ بِمَا قَدَّمَ وَأَخَّرَ
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun tó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
Arabic explanations of the Qur’an:
بَلِ ٱلۡإِنسَٰنُ عَلَىٰ نَفۡسِهِۦ بَصِيرَةٞ
Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَوۡ أَلۡقَىٰ مَعَاذِيرَهُۥ
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
Arabic explanations of the Qur’an:
لَا تُحَرِّكۡ بِهِۦ لِسَانَكَ لِتَعۡجَلَ بِهِۦٓ
Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّ عَلَيۡنَا جَمۡعَهُۥ وَقُرۡءَانَهُۥ
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَإِذَا قَرَأۡنَٰهُ فَٱتَّبِعۡ قُرۡءَانَهُۥ
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ إِنَّ عَلَيۡنَا بَيَانَهُۥ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّا بَلۡ تُحِبُّونَ ٱلۡعَاجِلَةَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé ni.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَتَذَرُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Ẹ sì ń gbé ọ̀run jù sílẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ نَّاضِرَةٌ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
Arabic explanations of the Qur’an:
إِلَىٰ رَبِّهَا نَاظِرَةٞ
Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَوُجُوهٞ يَوۡمَئِذِۭ بَاسِرَةٞ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
Arabic explanations of the Qur’an:
تَظُنُّ أَن يُفۡعَلَ بِهَا فَاقِرَةٞ
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé wọ́n máa fi aburú kan òhun.
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّآ إِذَا بَلَغَتِ ٱلتَّرَاقِيَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَقِيلَ مَنۡۜ رَاقٖ
A sì máa sọ pé: “Ǹjẹ́ olùpọfọ̀ kan wà bí (tí ó máa pọfọ̀ láti gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
Arabic explanations of the Qur’an:
وَظَنَّ أَنَّهُ ٱلۡفِرَاقُ
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱلۡتَفَّتِ ٱلسَّاقُ بِٱلسَّاقِ
Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمَسَاقُ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَلَا صَدَّقَ وَلَا صَلَّىٰ
Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَٰكِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰ
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo ní irọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ ذَهَبَ إِلَىٰٓ أَهۡلِهِۦ يَتَمَطَّىٰٓ
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
Arabic explanations of the Qur’an:
أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰ
(Ìparun nílé ayé) ló tọ́ sí ọ jùlọ (lórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ wọ̀nyẹn). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰٓ
Lẹ́yìn náà, (Iná) ló tọ́ sí ọ jùlọ (ní ọ̀run). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
Arabic explanations of the Qur’an:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَن يُتۡرَكَ سُدًى
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
Arabic explanations of the Qur’an:
أَلَمۡ يَكُ نُطۡفَةٗ مِّن مَّنِيّٖ يُمۡنَىٰ
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
Arabic explanations of the Qur’an:
ثُمَّ كَانَ عَلَقَةٗ فَخَلَقَ فَسَوَّىٰ
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é tó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَجَعَلَ مِنۡهُ ٱلزَّوۡجَيۡنِ ٱلذَّكَرَ وَٱلۡأُنثَىٰٓ
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti ara rẹ̀, akọ àti abo.
Arabic explanations of the Qur’an:
أَلَيۡسَ ذَٰلِكَ بِقَٰدِرٍ عَلَىٰٓ أَن يُحۡـِۧيَ ٱلۡمَوۡتَىٰ
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Surah: Al-Qiyāmah
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close