Tradução dos significados do Nobre Qur’an. - Tradução européia * - Índice de tradução

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Tradução dos significados Surah: Suratu Al-Fajr   Versículo:

Suuratul-Faj'r

وَٱلۡفَجۡرِ
Allāhu fi àfẹ̀mọ́júmọ́ búra.
Os Tafssir em língua árabe:
وَلَيَالٍ عَشۡرٖ
Ó tún fi àwọn òru mẹ́wàá kan búra.
Os Tafssir em língua árabe:
وَٱلشَّفۡعِ وَٱلۡوَتۡرِ
Ó tún fi n̄ǹkan tí eéjì ń pín geerege àti n̄ǹkan tí eéjì kò pín geerege búra.
Os Tafssir em língua árabe:
وَٱلَّيۡلِ إِذَا يَسۡرِ
Ó tún fi òru nígbà tí ó bá dé búra.
Os Tafssir em língua árabe:
هَلۡ فِي ذَٰلِكَ قَسَمٞ لِّذِي حِجۡرٍ
Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?
Os Tafssir em língua árabe:
أَلَمۡ تَرَ كَيۡفَ فَعَلَ رَبُّكَ بِعَادٍ
Ṣé o kò wòye sí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,
Os Tafssir em língua árabe:
إِرَمَ ذَاتِ ٱلۡعِمَادِ
(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,
Os Tafssir em língua árabe:
ٱلَّتِي لَمۡ يُخۡلَقۡ مِثۡلُهَا فِي ٱلۡبِلَٰدِ
àwọn tí A kò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?
Os Tafssir em língua árabe:
وَثَمُودَ ٱلَّذِينَ جَابُواْ ٱلصَّخۡرَ بِٱلۡوَادِ
Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonúfojì,
Os Tafssir em língua árabe:
وَفِرۡعَوۡنَ ذِي ٱلۡأَوۡتَادِ
àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?
Os Tafssir em língua árabe:
ٱلَّذِينَ طَغَوۡاْ فِي ٱلۡبِلَٰدِ
(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn tó tayọ ẹnu-ààlà nínú ìlú.
Os Tafssir em língua árabe:
فَأَكۡثَرُواْ فِيهَا ٱلۡفَسَادَ
Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.
Os Tafssir em língua árabe:
فَصَبَّ عَلَيۡهِمۡ رَبُّكَ سَوۡطَ عَذَابٍ
Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.
Os Tafssir em língua árabe:
إِنَّ رَبَّكَ لَبِٱلۡمِرۡصَادِ
Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).
Os Tafssir em língua árabe:
فَأَمَّا ٱلۡإِنسَٰنُ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ رَبُّهُۥ فَأَكۡرَمَهُۥ وَنَعَّمَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَكۡرَمَنِ
Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti pọ́n mi lé.”
Os Tafssir em língua árabe:
وَأَمَّآ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ فَقَدَرَ عَلَيۡهِ رِزۡقَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَهَٰنَنِ
Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi.”
Os Tafssir em língua árabe:
كَلَّاۖ بَل لَّا تُكۡرِمُونَ ٱلۡيَتِيمَ
Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.
Os Tafssir em língua árabe:
وَلَا تَحَٰٓضُّونَ عَلَىٰ طَعَامِ ٱلۡمِسۡكِينِ
Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.
Os Tafssir em língua árabe:
وَتَأۡكُلُونَ ٱلتُّرَاثَ أَكۡلٗا لَّمّٗا
Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.
Os Tafssir em língua árabe:
وَتُحِبُّونَ ٱلۡمَالَ حُبّٗا جَمّٗا
Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.
Os Tafssir em língua árabe:
كَلَّآۖ إِذَا دُكَّتِ ٱلۡأَرۡضُ دَكّٗا دَكّٗا
Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (tó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),
Os Tafssir em língua árabe:
وَجَآءَ رَبُّكَ وَٱلۡمَلَكُ صَفّٗا صَفّٗا
(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,
Os Tafssir em língua árabe:
وَجِاْيٓءَ يَوۡمَئِذِۭ بِجَهَنَّمَۚ يَوۡمَئِذٖ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ وَأَنَّىٰ لَهُ ٱلذِّكۡرَىٰ
ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!
Os Tafssir em língua árabe:
يَقُولُ يَٰلَيۡتَنِي قَدَّمۡتُ لِحَيَاتِي
Ó máa wí pé: “Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi.”
Os Tafssir em língua árabe:
فَيَوۡمَئِذٖ لَّا يُعَذِّبُ عَذَابَهُۥٓ أَحَدٞ
Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).
Os Tafssir em língua árabe:
وَلَا يُوثِقُ وَثَاقَهُۥٓ أَحَدٞ
Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).
Os Tafssir em língua árabe:
يَٰٓأَيَّتُهَا ٱلنَّفۡسُ ٱلۡمُطۡمَئِنَّةُ
Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,
Os Tafssir em língua árabe:
ٱرۡجِعِيٓ إِلَىٰ رَبِّكِ رَاضِيَةٗ مَّرۡضِيَّةٗ
padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.
Os Tafssir em língua árabe:
فَٱدۡخُلِي فِي عِبَٰدِي
Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.
Os Tafssir em língua árabe:
وَٱدۡخُلِي جَنَّتِي
Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.
Os Tafssir em língua árabe:
 
Tradução dos significados Surah: Suratu Al-Fajr
Índice de capítulos Número de página
 
Tradução dos significados do Nobre Qur’an. - Tradução européia - Índice de tradução

Tradução dos significados do Nobre Alcorão para a língua iorubá, traduzido pelo xeque Abu Rahima, Michael Ikoyeni. Edição do ano 1432 AH

Fechar