《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 * - 译解目录

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

含义的翻译 段: (66) 章: 优努斯
أَلَآ إِنَّ لِلَّهِ مَن فِي ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَمَن فِي ٱلۡأَرۡضِۗ وَمَا يَتَّبِعُ ٱلَّذِينَ يَدۡعُونَ مِن دُونِ ٱللَّهِ شُرَكَآءَۚ إِن يَتَّبِعُونَ إِلَّا ٱلظَّنَّ وَإِنۡ هُمۡ إِلَّا يَخۡرُصُونَ
Gbọ́, dájúdájú ti Allāhu ni ẹnikẹ́ni tó ń bẹ nínú àwọn sánmọ̀ àti ẹnikẹ́ni tó ń bẹ lórí ilẹ̀. Àwọn tó ń pe àwọn òrìṣà lẹ́yìn Allāhu kò (rí) akẹgbẹ́ Allāhu tẹ̀lé (torí pé, kò sí akẹgbẹ́ fún Allāhu níbìkan kan) Wọn kò tẹ̀lé (kiní kan) bí kò ṣe àbá dídá.¹ Wọn kò sì ṣe kiní kan bí kò ṣe pé wọ́n ń parọ́.
1. Fúnra wọn ni wọ́n rò wọ́n sí akẹgbẹ́ Allāhu, wọ́n dá a ní àbá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ lọ́dọ̀ ara wọn pé, “Ìwọ̀nyí ni akẹgbẹ́ fún Allāhu” Allāhu kò sì ní akẹgbẹ́. Bí àpẹ̀ẹrẹ, àwọn nasọ̄rọ̄ rò pé Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - ni “ọmọ Ọlọ́hun, ọlọ́hun ọmọ, olúwa àti olùgbàlà” Wọ́n dá a ní àbá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ́dọ̀ ara wọn. Kì í ṣe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - ló pe ara rẹ̀ bẹ́ẹ̀ fún wọn.
阿拉伯语经注:
 
含义的翻译 段: (66) 章: 优努斯
章节目录 页码
 
《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 - 译解目录

古兰经泰卢固语译解,艾布·拉赫曼·米卡伊里·艾库比尼长老翻译,伊历1432年出版发行。

关闭