Báyẹn sì ni A ṣe fi ìmísí ránṣẹ́ sí ọ nínú àṣẹ Wa. Ìwọ kò mọ kí ni Tírà àti ìgbàgbọ́ òdodo tẹ́lẹ̀ (ṣíwájú ìmísí náà),¹ ṣùgbọ́n A ṣe ìmísí náà ní ìmọ́lẹ̀ kan tí À ń fi ṣe ìmọ̀nà fún ẹni tí A bá fẹ́ nínú àwọn ẹrúsìn Wa. Dájúdájú ìwọ ń pèpè sí ọ̀nà tààrà (’Islām).²
1. Āyah yìí ń fi kókó pàtàkì kan rinlẹ̀ nípa ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí ayé Ànábì wa Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - pé, ṣíwájú kí ìmísí mímọ́ tó bẹ̀rẹ̀ sí ṣọ̀kalẹ̀ fún un kò sí nínú ẹni tó nímọ̀ sí tírà sánmọ̀ kan kan, kò sì dá ìgbàgbọ́ òdodo mọ. Allāhu - tó ga jùlọ - tún fi èyí rinlẹ̀ bẹ́ẹ̀ nínú sūrah ad-Duhā; 93:7. Àmọ́ níkété tí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - bẹ̀rẹ̀ sí gba ìmísí mímọ́, Allāhu fi ìmọ̀ tírà al-Ƙur’ān àti ìgbàgbọ́ òdodo mọ̀ ọ́n. Ó sì di olùpèpè sínú ìmọ̀nà. Ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ àwọn Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun ni ìṣẹ̀mí ayé wọn rí bí Ànábì wa - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ti ṣe rí àfi ẹni tí bàbá rẹ̀ bá jẹ́ Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun.
Àmọ́ ṣá, kò sí abọ̀rìṣà kan tí Allāhu sọ di Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ Rẹ̀ rí. Ẹni tí Allāhu máa sọ di Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ lè má tí ì mọ tírà nígbà tí Ọlọ́hun kò ì tí ì fún un, ó sì lè má tí ì dá ìgbàgbọ́ òdodo mọ̀, nígbà tí Ọlọ́hun kò tí ì ròyìn Ara Rẹ̀ fún un, àmọ́ kò níí sí nínú àwọn ọ̀ṣẹbọ tàbí àwọn òbìlẹ̀jẹ́ ènìyàn. Kódà, láti kékeré wọn ni Allāhu - Ọba mímọ́ - ti máa ń jogún òye fún wọn pé, “irọ́ ni òrìṣà” títí àsìkò ìmísí wọn yóò fi dé bá wọn.
Síwájú sí i, tí ẹnì kan bá sì sọ pé, iṣẹ́ wiridi ni Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - máa ń ṣe nínú ọ̀gbun Hirā ṣíwájú kí ó tó di Ànábì Ọlọ́hun, irọ́ l’ó fi pa. Ìdí ni pé, ẹnì kan kì í ṣe wiridi láì gbọwọ́, ta ni ó fún Ànábì lọ́wọ́ wiridi? Kò sí.
Bákan náà, kò sí ojú ọ̀nà wiridi tí kò lórúkọ, kí ni orúkọ tọrikọ sūfī tí Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ṣe? Kò sí.
Èyí tó wá kó ọ̀rọ̀ tán nílẹ̀ ni pé, títẹ̀lé Muhammad ọmọ ‘Abdullah - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, kò di ẹ̀sìn àfi láti àsìkò tí ó di Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun. Kò sì lọ sínú ọ̀gbun Hirā mọ́ bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí mọlāika Jibrīl - kí ọlà Allāhu máa bá a - ti fún un ní ìmísí àkọ́kọ́. Nítorí náà, Ànábì kì í ṣe sūfī, kò sì ṣe wiridi sūfī rí.
2. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Ƙọsọs; 28:56.
Contents of the translations can be downloaded and re-published, with the following terms and conditions:
1. No modification, addition, or deletion of the content.
2. Clearly referring to the publisher and the source (QuranEnc.com).
3. Mentioning the version number when re-publishing the translation.
4. Keeping the transcript information inside the document.
5. Notifying the source (QuranEnc.com) of any note on the translation.
6. Updating the translation according to the latest version issued from the source (QuranEnc.com).
7. Inappropriate advertisements must not be included when displaying translations of the meanings of the Noble Quran.
搜索结果:
API specs
Endpoints:
Sura translation
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/sura/{translation_key}/{sura_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified sura (by its number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114)
Returns:
json object containing array of objects, each object contains the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".
GET / https://quranenc.com/api/v1/translation/aya/{translation_key}/{sura_number}/{aya_number} description: get the specified translation (by its translation_key) for the speicified aya (by its number sura_number and aya_number)
Parameters: translation_key: (the key of the currently selected translation) sura_number: [1-114] (Sura number in the mosshaf which should be between 1 and 114) aya_number: [1-...] (Aya number in the sura)
Returns:
json object containing the "sura", "aya", "translation" and "footnotes".