《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 * - 译解目录

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

含义的翻译 段: (32) 章: 杜哈尼
وَلَقَدِ ٱخۡتَرۡنَٰهُمۡ عَلَىٰ عِلۡمٍ عَلَى ٱلۡعَٰلَمِينَ
A kúkú ṣà wọ́n lẹ́ṣà lórí àwọn ẹ̀dá (àsìkò tiwọn) pẹ̀lú ìmọ̀ (tí a mọ̀ nípa wọn).¹
1 “pẹ̀lú ìmọ̀” ní àyè yìí túmọ̀ sí pé, ṣíṣa àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl lẹ́ṣà lórí àwọn ẹ̀dá, ó ti wà nínú ìmọ̀ Allāhu - Ọba Alámọ̀tán - nípa wọn ṣíwájú ìṣẹ̀dá wọn. Nítorí náà, àwọn tí Allāhu ṣe ní Ànábì àti Òjíṣẹ́ Rẹ̀ nínú wọn, kì í ṣe àṣìmú tàbí àṣìyàn bí kò ṣe àṣàyàn ẹ̀dá. Irú āyah yìí ni ọ̀rọ̀ Allāhu tó sọ pé: “Allāhu ló nímọ̀ jùlọ nípa ibi tí Ó ń fí iṣẹ́-rírán Rẹ̀ sí.” Sūrah al-’Ani‘ām; 6:124
Bákan náà, “lórí àwọn ẹ̀dá” ní àyè yìí túmọ̀ sí àwọn ẹ̀dá ìgbà tiwọn.
Àmọ́ lẹ́yìn ìgbédìde Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, ìjọ rẹ̀ ni Allāhu tún ṣà lẹ́ṣà lórí àwọn ọmọ ’Isrọ̄’īl àti àwọn ènìyàn yòókù pátápátá. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:110.
Kíyè sí i, ibikíbi nínú al-Ƙur’ān tí Allāhu bá ti sọ pé, Òun ṣa àwọn ẹ̀dá kan lẹ́ṣà lórí àwọn ẹ̀dá mìíràn, ó dúró fún àwọn ẹ̀dá ìgbà tiwọn nìkan. Ìṣàlẹ́ṣà náà kò sì kan àwọn ará ìgbà mìíràn. Ẹ wo sūrah al-Baƙọrah; 2:47 àti 122, sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:33, sūrah al-’Ani‘ām; 6:86, sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:140 àti sūrah al-Jāthiyah; 45:16.
阿拉伯语经注:
 
含义的翻译 段: (32) 章: 杜哈尼
章节目录 页码
 
《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 - 译解目录

古兰经泰卢固语译解,艾布·拉赫曼·米卡伊里·艾库比尼长老翻译,伊历1432年出版发行。

关闭