《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 * - 译解目录

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

含义的翻译 章: 阿拜萨   段:

Suuratu Abasa

عَبَسَ وَتَوَلَّىٰٓ
Ó fajú ro, ó sì pẹ̀yìndà¹
1. Ìyẹn ni pé, Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - fajú ro, ó sì pẹ̀yìndà.
阿拉伯语经注:
أَن جَآءَهُ ٱلۡأَعۡمَىٰ
nítorí pé afọ́jú wá bá a.
阿拉伯语经注:
وَمَا يُدۡرِيكَ لَعَلَّهُۥ يَزَّكَّىٰٓ
Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)
阿拉伯语经注:
أَوۡ يَذَّكَّرُ فَتَنفَعَهُ ٱلذِّكۡرَىٰٓ
tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?
阿拉伯语经注:
أَمَّا مَنِ ٱسۡتَغۡنَىٰ
Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,
阿拉伯语经注:
فَأَنتَ لَهُۥ تَصَدَّىٰ
òun ni ìwọ tẹ́tí sí.
阿拉伯语经注:
وَمَا عَلَيۡكَ أَلَّا يَزَّكَّىٰ
Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).
阿拉伯语经注:
وَأَمَّا مَن جَآءَكَ يَسۡعَىٰ
Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, tó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú),
阿拉伯语经注:
وَهُوَ يَخۡشَىٰ
tí ó sì ń páyà (Allāhu),
阿拉伯语经注:
فَأَنتَ عَنۡهُ تَلَهَّىٰ
ìwọ kò sì kọbi ara sí i.
阿拉伯语经注:
كَلَّآ إِنَّهَا تَذۡكِرَةٞ
Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
阿拉伯语经注:
فَمَن شَآءَ ذَكَرَهُۥ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.
阿拉伯语经注:
فِي صُحُفٖ مُّكَرَّمَةٖ
(Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,
阿拉伯语经注:
مَّرۡفُوعَةٖ مُّطَهَّرَةِۭ
A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́
阿拉伯语经注:
بِأَيۡدِي سَفَرَةٖ
ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika),
阿拉伯语经注:
كِرَامِۭ بَرَرَةٖ
àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.
阿拉伯语经注:
قُتِلَ ٱلۡإِنسَٰنُ مَآ أَكۡفَرَهُۥ
Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!
阿拉伯语经注:
مِنۡ أَيِّ شَيۡءٍ خَلَقَهُۥ
Kí sì ni Allāhu fi ṣẹ̀dá rẹ̀?
阿拉伯语经注:
مِن نُّطۡفَةٍ خَلَقَهُۥ فَقَدَّرَهُۥ
Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ ٱلسَّبِيلَ يَسَّرَهُۥ
Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ أَمَاتَهُۥ فَأَقۡبَرَهُۥ
Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ إِذَا شَآءَ أَنشَرَهُۥ
Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.
阿拉伯语经注:
كَلَّا لَمَّا يَقۡضِ مَآ أَمَرَهُۥ
Rárá o! Ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un.
阿拉伯语经注:
فَلۡيَنظُرِ ٱلۡإِنسَٰنُ إِلَىٰ طَعَامِهِۦٓ
Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.
阿拉伯语经注:
أَنَّا صَبَبۡنَا ٱلۡمَآءَ صَبّٗا
Dájúdájú Àwa ń rọ òjò ní púpọ̀.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ شَقَقۡنَا ٱلۡأَرۡضَ شَقّٗا
Lẹ́yìn náà, A mú ilẹ̀ sán kànkàn.
阿拉伯语经注:
فَأَنۢبَتۡنَا فِيهَا حَبّٗا
A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;
阿拉伯语经注:
وَعِنَبٗا وَقَضۡبٗا
àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,
阿拉伯语经注:
وَزَيۡتُونٗا وَنَخۡلٗا
àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù,
阿拉伯语经注:
وَحَدَآئِقَ غُلۡبٗا
àti àwọn ọgbà tó kún fún igi,
阿拉伯语经注:
وَفَٰكِهَةٗ وَأَبّٗا
àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).
阿拉伯语经注:
مَّتَٰعٗا لَّكُمۡ وَلِأَنۡعَٰمِكُمۡ
(Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
阿拉伯语经注:
فَإِذَا جَآءَتِ ٱلصَّآخَّةُ
Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,
阿拉伯语经注:
يَوۡمَ يَفِرُّ ٱلۡمَرۡءُ مِنۡ أَخِيهِ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,
阿拉伯语经注:
وَأُمِّهِۦ وَأَبِيهِ
àti ìyá rẹ̀ àti bàbá rẹ̀,
阿拉伯语经注:
وَصَٰحِبَتِهِۦ وَبَنِيهِ
àti ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
阿拉伯语经注:
لِكُلِّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ يَوۡمَئِذٖ شَأۡنٞ يُغۡنِيهِ
Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn tó máa tó o ó rán.
阿拉伯语经注:
وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ مُّسۡفِرَةٞ
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.
阿拉伯语经注:
ضَاحِكَةٞ مُّسۡتَبۡشِرَةٞ
Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.
阿拉伯语经注:
وَوُجُوهٞ يَوۡمَئِذٍ عَلَيۡهَا غَبَرَةٞ
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.
阿拉伯语经注:
تَرۡهَقُهَا قَتَرَةٌ
Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.
阿拉伯语经注:
أُوْلَٰٓئِكَ هُمُ ٱلۡكَفَرَةُ ٱلۡفَجَرَةُ
Àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
阿拉伯语经注:
 
含义的翻译 章: 阿拜萨
章节目录 页码
 
《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 - 译解目录

古兰经泰卢固语译解,艾布·拉赫曼·米卡伊里·艾库比尼长老翻译,伊历1432年出版发行。

关闭