ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية * - فهرس التراجم

PDF XML CSV Excel API
تنزيل الملفات يتضمن الموافقة على هذه الشروط والسياسات

ترجمة معاني سورة: المدثر   آية:

سورة المدثر - Suuratul-Muddathir

يَٰٓأَيُّهَا ٱلۡمُدَّثِّرُ
Ìwọ olùdaṣọbora.
التفاسير العربية:
قُمۡ فَأَنذِرۡ
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
التفاسير العربية:
وَرَبَّكَ فَكَبِّرۡ
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
التفاسير العربية:
وَثِيَابَكَ فَطَهِّرۡ
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
التفاسير العربية:
وَٱلرُّجۡزَ فَٱهۡجُرۡ
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
التفاسير العربية:
وَلَا تَمۡنُن تَسۡتَكۡثِرُ
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
التفاسير العربية:
وَلِرَبِّكَ فَٱصۡبِرۡ
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
التفاسير العربية:
فَإِذَا نُقِرَ فِي ٱلنَّاقُورِ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
التفاسير العربية:
فَذَٰلِكَ يَوۡمَئِذٖ يَوۡمٌ عَسِيرٌ
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
التفاسير العربية:
عَلَى ٱلۡكَٰفِرِينَ غَيۡرُ يَسِيرٖ
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
التفاسير العربية:
ذَرۡنِي وَمَنۡ خَلَقۡتُ وَحِيدٗا
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan (ìyẹn nínú ikùn ìyá rẹ̀).
التفاسير العربية:
وَجَعَلۡتُ لَهُۥ مَالٗا مَّمۡدُودٗا
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
التفاسير العربية:
وَبَنِينَ شُهُودٗا
àti àwọn ọmọkúnrin tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
التفاسير العربية:
وَمَهَّدتُّ لَهُۥ تَمۡهِيدٗا
Mo sì fi àyè ìrọ̀rùn gbá a dáadáa.
التفاسير العربية:
ثُمَّ يَطۡمَعُ أَنۡ أَزِيدَ
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
التفاسير العربية:
كَلَّآۖ إِنَّهُۥ كَانَ لِأٓيَٰتِنَا عَنِيدٗا
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
التفاسير العربية:
سَأُرۡهِقُهُۥ صَعُودًا
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná)¹.
[1] Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
التفاسير العربية:
إِنَّهُۥ فَكَّرَ وَقَدَّرَ
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
التفاسير العربية:
فَقُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
التفاسير العربية:
ثُمَّ قُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
التفاسير العربية:
ثُمَّ نَظَرَ
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
التفاسير العربية:
ثُمَّ عَبَسَ وَبَسَرَ
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
التفاسير العربية:
ثُمَّ أَدۡبَرَ وَٱسۡتَكۡبَرَ
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìndà, ó sì ṣègbéraga.
التفاسير العربية:
فَقَالَ إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا سِحۡرٞ يُؤۡثَرُ
Ó sì wí pé: “Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
التفاسير العربية:
إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا قَوۡلُ ٱلۡبَشَرِ
Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara”
التفاسير العربية:
سَأُصۡلِيهِ سَقَرَ
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
التفاسير العربية:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا سَقَرُ
Kí l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ iná Saƙọr?
التفاسير العربية:
لَا تُبۡقِي وَلَا تَذَرُ
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.¹
1. Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
التفاسير العربية:
لَوَّاحَةٞ لِّلۡبَشَرِ
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
التفاسير العربية:
عَلَيۡهَا تِسۡعَةَ عَشَرَ
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
التفاسير العربية:
وَمَا جَعَلۡنَآ أَصۡحَٰبَ ٱلنَّارِ إِلَّا مَلَٰٓئِكَةٗۖ وَمَا جَعَلۡنَا عِدَّتَهُمۡ إِلَّا فِتۡنَةٗ لِّلَّذِينَ كَفَرُواْ لِيَسۡتَيۡقِنَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَيَزۡدَادَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُوٓاْ إِيمَٰنٗا وَلَا يَرۡتَابَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَٱلۡمُؤۡمِنُونَ وَلِيَقُولَ ٱلَّذِينَ فِي قُلُوبِهِم مَّرَضٞ وَٱلۡكَٰفِرُونَ مَاذَآ أَرَادَ ٱللَّهُ بِهَٰذَا مَثَلٗاۚ كَذَٰلِكَ يُضِلُّ ٱللَّهُ مَن يَشَآءُ وَيَهۡدِي مَن يَشَآءُۚ وَمَا يَعۡلَمُ جُنُودَ رَبِّكَ إِلَّا هُوَۚ وَمَا هِيَ إِلَّا ذِكۡرَىٰ لِلۡبَشَرِ
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: “Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?” Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
التفاسير العربية:
كَلَّا وَٱلۡقَمَرِ
Ẹ gbọ́! Allāhu fi òṣùpá búra.
التفاسير العربية:
وَٱلَّيۡلِ إِذۡ أَدۡبَرَ
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.
التفاسير العربية:
وَٱلصُّبۡحِ إِذَآ أَسۡفَرَ
Ó tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́ búra.
التفاسير العربية:
إِنَّهَا لَإِحۡدَى ٱلۡكُبَرِ
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) tó tóbi.
التفاسير العربية:
نَذِيرٗا لِّلۡبَشَرِ
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
التفاسير العربية:
لِمَن شَآءَ مِنكُمۡ أَن يَتَقَدَّمَ أَوۡ يَتَأَخَّرَ
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn (nínú ẹ̀ṣẹ̀).
التفاسير العربية:
كُلُّ نَفۡسِۭ بِمَا كَسَبَتۡ رَهِينَةٌ
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun tó ṣe níṣẹ́.
التفاسير العربية:
إِلَّآ أَصۡحَٰبَ ٱلۡيَمِينِ
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
التفاسير العربية:
فِي جَنَّٰتٖ يَتَسَآءَلُونَ
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
التفاسير العربية:
عَنِ ٱلۡمُجۡرِمِينَ
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
التفاسير العربية:
مَا سَلَكَكُمۡ فِي سَقَرَ
“Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?”
التفاسير العربية:
قَالُواْ لَمۡ نَكُ مِنَ ٱلۡمُصَلِّينَ
Wọn yóò wí pé: “Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
التفاسير العربية:
وَلَمۡ نَكُ نُطۡعِمُ ٱلۡمِسۡكِينَ
Àwa kò sì sí nínú àwọn tó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
التفاسير العربية:
وَكُنَّا نَخُوضُ مَعَ ٱلۡخَآئِضِينَ
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
التفاسير العربية:
وَكُنَّا نُكَذِّبُ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́
التفاسير العربية:
حَتَّىٰٓ أَتَىٰنَا ٱلۡيَقِينُ
títí ikú fi dé bá wa.”
التفاسير العربية:
فَمَا تَنفَعُهُمۡ شَفَٰعَةُ ٱلشَّٰفِعِينَ
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
التفاسير العربية:
فَمَا لَهُمۡ عَنِ ٱلتَّذۡكِرَةِ مُعۡرِضِينَ
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
التفاسير العربية:
كَأَنَّهُمۡ حُمُرٞ مُّسۡتَنفِرَةٞ
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń sá lọ,
التفاسير العربية:
فَرَّتۡ مِن قَسۡوَرَةِۭ
tó sá fún kìnìhún?
التفاسير العربية:
بَلۡ يُرِيدُ كُلُّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ أَن يُؤۡتَىٰ صُحُفٗا مُّنَشَّرَةٗ
Rárá, ńṣe ni ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
التفاسير العربية:
كَلَّاۖ بَل لَّا يَخَافُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.
التفاسير العربية:
كَلَّآ إِنَّهُۥ تَذۡكِرَةٞ
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
التفاسير العربية:
فَمَن شَآءَ ذَكَرَهُۥ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́, kí ó rántí rẹ̀.
التفاسير العربية:
وَمَا يَذۡكُرُونَ إِلَّآ أَن يَشَآءَ ٱللَّهُۚ هُوَ أَهۡلُ ٱلتَّقۡوَىٰ وَأَهۡلُ ٱلۡمَغۡفِرَةِ
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì ni àforíjìn.
التفاسير العربية:
 
ترجمة معاني سورة: المدثر
فهرس السور رقم الصفحة
 
ترجمة معاني القرآن الكريم - الترجمة اليورباوية - فهرس التراجم

ترجمة معاني القرآن الكريم إلى اللغة اليوربا، ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني. طبعة عام 1432هـ .

إغلاق