Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung * - Übersetzungen

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: Al-Ma‘ârij   Vers:

Suuratul-Mahaarij

سَأَلَ سَآئِلُۢ بِعَذَابٖ وَاقِعٖ
Oníbèéèrè kan bèèrè nípa ìyà tó máa ṣẹlẹ̀
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لِّلۡكَٰفِرِينَ لَيۡسَ لَهُۥ دَافِعٞ
sí àwọn aláìgbàgbọ́. Kò sì sí ẹni tí ó máa dí i lọ́wọ́
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
مِّنَ ٱللَّهِ ذِي ٱلۡمَعَارِجِ
lọ́dọ̀ Allāhu, Onípò-àyè gíga.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
تَعۡرُجُ ٱلۡمَلَٰٓئِكَةُ وَٱلرُّوحُ إِلَيۡهِ فِي يَوۡمٖ كَانَ مِقۡدَارُهُۥ خَمۡسِينَ أَلۡفَ سَنَةٖ
Àwọn mọlāika àti mọlāika Jibrīl ń gùnkè wá sí ọ̀dọ̀ Rẹ̀ nínú ọjọ́ kan tí òdiwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún (tí ẹ bá fẹ́ rìn ín).¹
1. Ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún ni ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta ọdún (50,000). Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Hajj; 22:47.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَٱصۡبِرۡ صَبۡرٗا جَمِيلًا
Nítorí náà, ṣe sùúrù ní sùúrù tó rẹwà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّهُمۡ يَرَوۡنَهُۥ بَعِيدٗا
Dájúdájú wọ́n ń wo (ìyà náà) ní ohun tó jìnnà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَنَرَىٰهُ قَرِيبٗا
A sì ń wò ó ní ohun tó súnmọ́.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
يَوۡمَ تَكُونُ ٱلسَّمَآءُ كَٱلۡمُهۡلِ
(Ọjọ́ náà ni) ọjọ́ tí sánmọ̀ yó dà bí ògéré epo gbígbóná,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَتَكُونُ ٱلۡجِبَالُ كَٱلۡعِهۡنِ
àwọn àpáta yó sì dà bí ẹ̀gbọ̀n òwú-irun,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَلَا يَسۡـَٔلُ حَمِيمٌ حَمِيمٗا
ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ kan kò sì níí bèèrè ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ (rẹ̀).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
يُبَصَّرُونَهُمۡۚ يَوَدُّ ٱلۡمُجۡرِمُ لَوۡ يَفۡتَدِي مِنۡ عَذَابِ يَوۡمِئِذِۭ بِبَنِيهِ
Wọ́n máa rí ara wọn (wọ́n sì máa dára wọn mọ̀). Ẹlẹ́ṣẹ̀ sì máa fẹ́ kí òun fi àwọn ọmọ rẹ̀ ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà ní ọjọ́ yẹn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَصَٰحِبَتِهِۦ وَأَخِيهِ
Ìyàwó rẹ̀ àti arákùnrin rẹ̀,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَفَصِيلَتِهِ ٱلَّتِي تُـٔۡوِيهِ
àti àwọn ẹbí rẹ̀ tó pa tì, tí àwọn sì ń gbà á sọ́dọ̀ nílé ayé,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَمَن فِي ٱلۡأَرۡضِ جَمِيعٗا ثُمَّ يُنجِيهِ
àti gbogbo ẹni tó wà lórí ilẹ̀ ayé pátápátá, (ó máa fẹ́ fi wọ́n ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà). Lẹ́yìn náà, (ó máa fẹ́) kí Allāhu gba òun là (nínú ìyà Iná).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَلَّآۖ إِنَّهَا لَظَىٰ
Rárá! Dájúdájú (ó máa wọ) iná Laṭḥọ̄ (iná tó ń jò fòfò).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
نَزَّاعَةٗ لِّلشَّوَىٰ
Ó máa bó awọ orí tòró.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
تَدۡعُواْ مَنۡ أَدۡبَرَ وَتَوَلَّىٰ
(Iná) yó máa ké sí ẹni tó kẹ̀yìn sí (ìgbágbọ́ òdodo), tí ó sì takété sí i,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَجَمَعَ فَأَوۡعَىٰٓ
ó kó (ọrọ̀) jọ, ó sì fi pamọ́ (kò ná an fún ẹ̀sìn).
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
۞ إِنَّ ٱلۡإِنسَٰنَ خُلِقَ هَلُوعًا
Dájúdájú ènìyàn, A ṣẹ̀dá rẹ̀ ní aláìlọ́kàn, ọ̀kánjúà.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِذَا مَسَّهُ ٱلشَّرُّ جَزُوعٗا
Nígbà tí aburú bá fọwọ́ bà á, ó máa kanra gógó.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَإِذَا مَسَّهُ ٱلۡخَيۡرُ مَنُوعًا
Nígbà tí ọwọ́ rẹ̀ bá sì ba oore, ó máa yahun.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِلَّا ٱلۡمُصَلِّينَ
Àyàfi àwọn olùkírun,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
ٱلَّذِينَ هُمۡ عَلَىٰ صَلَاتِهِمۡ دَآئِمُونَ
àwọn tí wọ́n dúnnímọ́ ìrun wọn;
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّذِينَ فِيٓ أَمۡوَٰلِهِمۡ حَقّٞ مَّعۡلُومٞ
àwọn tó mọ ojúṣe (wọn) nínú dúkìá wọn
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
لِّلسَّآئِلِ وَٱلۡمَحۡرُومِ
sí alágbe àti ẹni tí A ṣe arísìkí ní èèwọ̀ fún;
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّذِينَ يُصَدِّقُونَ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
àwọn tó ń gba ọjọ́ ẹ̀san gbọ́ ní òdodo;
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّذِينَ هُم مِّنۡ عَذَابِ رَبِّهِم مُّشۡفِقُونَ
àwọn tó ń páyà ìyà Olúwa wọn,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِنَّ عَذَابَ رَبِّهِمۡ غَيۡرُ مَأۡمُونٖ
dájúdájú ìyà Olúwa wọn kò ṣeé fàyàbalẹ̀ sí;
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ لِفُرُوجِهِمۡ حَٰفِظُونَ
àwọn tó ń ṣọ́ abẹ́ wọn,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
إِلَّا عَلَىٰٓ أَزۡوَٰجِهِمۡ أَوۡ مَا مَلَكَتۡ أَيۡمَٰنُهُمۡ فَإِنَّهُمۡ غَيۡرُ مَلُومِينَ
àyàfi lọ́dọ̀ àwọn ìyàwó wọn tàbí ẹrúbìnrin wọn ni wọn kò ti lè jẹ́ ẹni-èébú,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَمَنِ ٱبۡتَغَىٰ وَرَآءَ ذَٰلِكَ فَأُوْلَٰٓئِكَ هُمُ ٱلۡعَادُونَ
nítorí náà, ẹnikẹ́ni tó bá ń wá n̄ǹkan mìíràn lẹ́yìn ìyẹn, àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni olùtayọ-ẹnu ààlà;
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ لِأَمَٰنَٰتِهِمۡ وَعَهۡدِهِمۡ رَٰعُونَ
àwọn tó ń ṣọ́ àgbàfipamọ́ wọn àti àdéhùn wọn;
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّذِينَ هُم بِشَهَٰدَٰتِهِمۡ قَآئِمُونَ
àwọn tó ń dúró ti ìjẹ́rìí (òdodo) wọn;
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ عَلَىٰ صَلَاتِهِمۡ يُحَافِظُونَ
àti àwọn tó ń ṣọ́ àwọn ìrun wọn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أُوْلَٰٓئِكَ فِي جَنَّٰتٖ مُّكۡرَمُونَ
Àwọn wọ̀nyẹn ni alápọ̀n-ọ́nlé nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَمَالِ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ قِبَلَكَ مُهۡطِعِينَ
Kí ló mú àwọn tí kò gbàgbọ́ tí ara wọn kò balẹ̀ níwájú rẹ,
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَنِ ٱلۡيَمِينِ وَعَنِ ٱلشِّمَالِ عِزِينَ
tí wọ́n sì jókòó ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí sí ọwọ́ ọ̀tún àti ọwọ́ òsì (rẹ)?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
أَيَطۡمَعُ كُلُّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ أَن يُدۡخَلَ جَنَّةَ نَعِيمٖ
Ṣé ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń jẹ̀rankàn pé A óò mú òun wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra ni?
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
كَلَّآۖ إِنَّا خَلَقۡنَٰهُم مِّمَّا يَعۡلَمُونَ
Rárá o! Dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá wọn láti inú ohun tí wọ́n mọ̀.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَلَآ أُقۡسِمُ بِرَبِّ ٱلۡمَشَٰرِقِ وَٱلۡمَغَٰرِبِ إِنَّا لَقَٰدِرُونَ
Nítorí náà, Èmi ń fi Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn àti àwọn ibùwọ̀ òòrùn¹ búra, dájúdájú Àwa ni Alágbára
1. Ìyẹn ni pé, Èmi, Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn àti ibùwọ̀ òòrùn ń fi ara Mi búra. Wòóore: Èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣriƙ” àti “mọgrib” nínú sūrah al-Muzzammil; 73:9 ni agbègbè ibùyọ òòrùn àti agbègbè ibùwọ̀ òòrùn. Èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣriƙọen” nínú sūrah ar-Rahmọ̄n; 55:17 ni ibùyọ òòrùn lásìkò ẹ̀rùn àti ibùyọ òòrùn lásìkò òjò. Bákan náà, “mọgribaen” ibùwọ̀ òòrùn lásìkò ẹ̀rùn àti ibùwọ̀ òòrùn lásìkò òjò. Bákan náà, èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣāriƙ àti mọgārib” ni àwọn ọgọ́sàn-án ibùyọ òòrùn àti ọgọ́sàn-án ibùwọ̀ òòrùn. (Tafsīr Bagawiy)
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
عَلَىٰٓ أَن نُّبَدِّلَ خَيۡرٗا مِّنۡهُمۡ وَمَا نَحۡنُ بِمَسۡبُوقِينَ
láti yí (ìrísí wọn) padà (ní ọjọ́ Àjíǹde) sí (ìrísí kan) tó máa dára ju (ìrísí) wọn (tayé). Kò sì sí ẹni tó lè dá Wa lágara.¹
1. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Ƙiyāmọh; 75:3-4.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
فَذَرۡهُمۡ يَخُوضُواْ وَيَلۡعَبُواْ حَتَّىٰ يُلَٰقُواْ يَوۡمَهُمُ ٱلَّذِي يُوعَدُونَ
Nítorí náà, fi wọ́n sílẹ̀ kí wọ́n máa sọ ìsọkúsọ (wọn), kí wọ́n sì máa ṣeré títí wọn yóò fi pàdé ọjọ́ wọn tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
يَوۡمَ يَخۡرُجُونَ مِنَ ٱلۡأَجۡدَاثِ سِرَاعٗا كَأَنَّهُمۡ إِلَىٰ نُصُبٖ يُوفِضُونَ
Ọjọ́ tí wọn yóò sáré jáde wéréwéré láti inú àwọn sàréè, wọn yó sì dà bí ẹni pé wọ́n ń yára lọ sídìí ohun àfojúsùn kan.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
خَٰشِعَةً أَبۡصَٰرُهُمۡ تَرۡهَقُهُمۡ ذِلَّةٞۚ ذَٰلِكَ ٱلۡيَوۡمُ ٱلَّذِي كَانُواْ يُوعَدُونَ
Ojú wọn yóò wálẹ̀. Ìyẹpẹrẹ máa bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ọjọ́ yẹn ni èyí tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.
Arabische Interpretationen von dem heiligen Quran:
 
Übersetzung der Bedeutungen Surah / Kapitel: Al-Ma‘ârij
Suren/ Kapiteln Liste Nummer der Seite
 
Übersetzung der Bedeutungen von dem heiligen Quran - Yorubische Übersetzung - Übersetzungen

Übersetzung der Quran-Bedeutung in Yoruba Sprache von Abu Rahima Mikhail Aikweiny in 1432 H.

Schließen