وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی * - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی المعارج   ئایه‌تی:

Suuratul-Mahaarij

سَأَلَ سَآئِلُۢ بِعَذَابٖ وَاقِعٖ
Oníbèéèrè kan bèèrè nípa ìyà tó máa ṣẹlẹ̀
تەفسیرە عەرەبیەکان:
لِّلۡكَٰفِرِينَ لَيۡسَ لَهُۥ دَافِعٞ
sí àwọn aláìgbàgbọ́. Kò sì sí ẹni tí ó máa dí i lọ́wọ́
تەفسیرە عەرەبیەکان:
مِّنَ ٱللَّهِ ذِي ٱلۡمَعَارِجِ
lọ́dọ̀ Allāhu, Onípò-àyè gíga.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
تَعۡرُجُ ٱلۡمَلَٰٓئِكَةُ وَٱلرُّوحُ إِلَيۡهِ فِي يَوۡمٖ كَانَ مِقۡدَارُهُۥ خَمۡسِينَ أَلۡفَ سَنَةٖ
Àwọn mọlāika àti mọlāika Jibrīl ń gùnkè wá sí ọ̀dọ̀ Rẹ̀ nínú ọjọ́ kan tí òdiwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún (tí ẹ bá fẹ́ rìn ín).¹
1. Ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún ni ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta ọdún (50,000). Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Hajj; 22:47.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَٱصۡبِرۡ صَبۡرٗا جَمِيلًا
Nítorí náà, ṣe sùúrù ní sùúrù tó rẹwà.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّهُمۡ يَرَوۡنَهُۥ بَعِيدٗا
Dájúdájú wọ́n ń wo (ìyà náà) ní ohun tó jìnnà.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَنَرَىٰهُ قَرِيبٗا
A sì ń wò ó ní ohun tó súnmọ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
يَوۡمَ تَكُونُ ٱلسَّمَآءُ كَٱلۡمُهۡلِ
(Ọjọ́ náà ni) ọjọ́ tí sánmọ̀ yó dà bí ògéré epo gbígbóná,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَتَكُونُ ٱلۡجِبَالُ كَٱلۡعِهۡنِ
àwọn àpáta yó sì dà bí ẹ̀gbọ̀n òwú-irun,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَلَا يَسۡـَٔلُ حَمِيمٌ حَمِيمٗا
ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ kan kò sì níí bèèrè ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ (rẹ̀).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
يُبَصَّرُونَهُمۡۚ يَوَدُّ ٱلۡمُجۡرِمُ لَوۡ يَفۡتَدِي مِنۡ عَذَابِ يَوۡمِئِذِۭ بِبَنِيهِ
Wọ́n máa rí ara wọn (wọ́n sì máa dára wọn mọ̀). Ẹlẹ́ṣẹ̀ sì máa fẹ́ kí òun fi àwọn ọmọ rẹ̀ ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà ní ọjọ́ yẹn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَصَٰحِبَتِهِۦ وَأَخِيهِ
Ìyàwó rẹ̀ àti arákùnrin rẹ̀,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَفَصِيلَتِهِ ٱلَّتِي تُـٔۡوِيهِ
àti àwọn ẹbí rẹ̀ tó pa tì, tí àwọn sì ń gbà á sọ́dọ̀ nílé ayé,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَمَن فِي ٱلۡأَرۡضِ جَمِيعٗا ثُمَّ يُنجِيهِ
àti gbogbo ẹni tó wà lórí ilẹ̀ ayé pátápátá, (ó máa fẹ́ fi wọ́n ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà). Lẹ́yìn náà, (ó máa fẹ́) kí Allāhu gba òun là (nínú ìyà Iná).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَلَّآۖ إِنَّهَا لَظَىٰ
Rárá! Dájúdájú (ó máa wọ) iná Laṭḥọ̄ (iná tó ń jò fòfò).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
نَزَّاعَةٗ لِّلشَّوَىٰ
Ó máa bó awọ orí tòró.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
تَدۡعُواْ مَنۡ أَدۡبَرَ وَتَوَلَّىٰ
(Iná) yó máa ké sí ẹni tó kẹ̀yìn sí (ìgbágbọ́ òdodo), tí ó sì takété sí i,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَجَمَعَ فَأَوۡعَىٰٓ
ó kó (ọrọ̀) jọ, ó sì fi pamọ́ (kò ná an fún ẹ̀sìn).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
۞ إِنَّ ٱلۡإِنسَٰنَ خُلِقَ هَلُوعًا
Dájúdájú ènìyàn, A ṣẹ̀dá rẹ̀ ní aláìlọ́kàn, ọ̀kánjúà.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِذَا مَسَّهُ ٱلشَّرُّ جَزُوعٗا
Nígbà tí aburú bá fọwọ́ bà á, ó máa kanra gógó.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَإِذَا مَسَّهُ ٱلۡخَيۡرُ مَنُوعًا
Nígbà tí ọwọ́ rẹ̀ bá sì ba oore, ó máa yahun.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِلَّا ٱلۡمُصَلِّينَ
Àyàfi àwọn olùkírun,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ٱلَّذِينَ هُمۡ عَلَىٰ صَلَاتِهِمۡ دَآئِمُونَ
àwọn tí wọ́n dúnnímọ́ ìrun wọn;
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّذِينَ فِيٓ أَمۡوَٰلِهِمۡ حَقّٞ مَّعۡلُومٞ
àwọn tó mọ ojúṣe (wọn) nínú dúkìá wọn
تەفسیرە عەرەبیەکان:
لِّلسَّآئِلِ وَٱلۡمَحۡرُومِ
sí alágbe àti ẹni tí A ṣe arísìkí ní èèwọ̀ fún;
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّذِينَ يُصَدِّقُونَ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
àwọn tó ń gba ọjọ́ ẹ̀san gbọ́ ní òdodo;
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّذِينَ هُم مِّنۡ عَذَابِ رَبِّهِم مُّشۡفِقُونَ
àwọn tó ń páyà ìyà Olúwa wọn,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّ عَذَابَ رَبِّهِمۡ غَيۡرُ مَأۡمُونٖ
dájúdájú ìyà Olúwa wọn kò ṣeé fàyàbalẹ̀ sí;
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ لِفُرُوجِهِمۡ حَٰفِظُونَ
àwọn tó ń ṣọ́ abẹ́ wọn,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِلَّا عَلَىٰٓ أَزۡوَٰجِهِمۡ أَوۡ مَا مَلَكَتۡ أَيۡمَٰنُهُمۡ فَإِنَّهُمۡ غَيۡرُ مَلُومِينَ
àyàfi lọ́dọ̀ àwọn ìyàwó wọn tàbí ẹrúbìnrin wọn ni wọn kò ti lè jẹ́ ẹni-èébú,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَمَنِ ٱبۡتَغَىٰ وَرَآءَ ذَٰلِكَ فَأُوْلَٰٓئِكَ هُمُ ٱلۡعَادُونَ
nítorí náà, ẹnikẹ́ni tó bá ń wá n̄ǹkan mìíràn lẹ́yìn ìyẹn, àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni olùtayọ-ẹnu ààlà;
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ لِأَمَٰنَٰتِهِمۡ وَعَهۡدِهِمۡ رَٰعُونَ
àwọn tó ń ṣọ́ àgbàfipamọ́ wọn àti àdéhùn wọn;
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّذِينَ هُم بِشَهَٰدَٰتِهِمۡ قَآئِمُونَ
àwọn tó ń dúró ti ìjẹ́rìí (òdodo) wọn;
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ عَلَىٰ صَلَاتِهِمۡ يُحَافِظُونَ
àti àwọn tó ń ṣọ́ àwọn ìrun wọn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
أُوْلَٰٓئِكَ فِي جَنَّٰتٖ مُّكۡرَمُونَ
Àwọn wọ̀nyẹn ni alápọ̀n-ọ́nlé nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَمَالِ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ قِبَلَكَ مُهۡطِعِينَ
Kí ló mú àwọn tí kò gbàgbọ́ tí ara wọn kò balẹ̀ níwájú rẹ,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
عَنِ ٱلۡيَمِينِ وَعَنِ ٱلشِّمَالِ عِزِينَ
tí wọ́n sì jókòó ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí sí ọwọ́ ọ̀tún àti ọwọ́ òsì (rẹ)?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
أَيَطۡمَعُ كُلُّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ أَن يُدۡخَلَ جَنَّةَ نَعِيمٖ
Ṣé ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń jẹ̀rankàn pé A óò mú òun wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra ni?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَلَّآۖ إِنَّا خَلَقۡنَٰهُم مِّمَّا يَعۡلَمُونَ
Rárá o! Dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá wọn láti inú ohun tí wọ́n mọ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَلَآ أُقۡسِمُ بِرَبِّ ٱلۡمَشَٰرِقِ وَٱلۡمَغَٰرِبِ إِنَّا لَقَٰدِرُونَ
Nítorí náà, Èmi ń fi Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn àti àwọn ibùwọ̀ òòrùn¹ búra, dájúdájú Àwa ni Alágbára
1. Ìyẹn ni pé, Èmi, Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn àti ibùwọ̀ òòrùn ń fi ara Mi búra. Wòóore: Èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣriƙ” àti “mọgrib” nínú sūrah al-Muzzammil; 73:9 ni agbègbè ibùyọ òòrùn àti agbègbè ibùwọ̀ òòrùn. Èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣriƙọen” nínú sūrah ar-Rahmọ̄n; 55:17 ni ibùyọ òòrùn lásìkò ẹ̀rùn àti ibùyọ òòrùn lásìkò òjò. Bákan náà, “mọgribaen” ibùwọ̀ òòrùn lásìkò ẹ̀rùn àti ibùwọ̀ òòrùn lásìkò òjò. Bákan náà, èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣāriƙ àti mọgārib” ni àwọn ọgọ́sàn-án ibùyọ òòrùn àti ọgọ́sàn-án ibùwọ̀ òòrùn. (Tafsīr Bagawiy)
تەفسیرە عەرەبیەکان:
عَلَىٰٓ أَن نُّبَدِّلَ خَيۡرٗا مِّنۡهُمۡ وَمَا نَحۡنُ بِمَسۡبُوقِينَ
láti yí (ìrísí wọn) padà (ní ọjọ́ Àjíǹde) sí (ìrísí kan) tó máa dára ju (ìrísí) wọn (tayé). Kò sì sí ẹni tó lè dá Wa lágara.¹
1. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Ƙiyāmọh; 75:3-4.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَذَرۡهُمۡ يَخُوضُواْ وَيَلۡعَبُواْ حَتَّىٰ يُلَٰقُواْ يَوۡمَهُمُ ٱلَّذِي يُوعَدُونَ
Nítorí náà, fi wọ́n sílẹ̀ kí wọ́n máa sọ ìsọkúsọ (wọn), kí wọ́n sì máa ṣeré títí wọn yóò fi pàdé ọjọ́ wọn tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
يَوۡمَ يَخۡرُجُونَ مِنَ ٱلۡأَجۡدَاثِ سِرَاعٗا كَأَنَّهُمۡ إِلَىٰ نُصُبٖ يُوفِضُونَ
Ọjọ́ tí wọn yóò sáré jáde wéréwéré láti inú àwọn sàréè, wọn yó sì dà bí ẹni pé wọ́n ń yára lọ sídìí ohun àfojúsùn kan.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
خَٰشِعَةً أَبۡصَٰرُهُمۡ تَرۡهَقُهُمۡ ذِلَّةٞۚ ذَٰلِكَ ٱلۡيَوۡمُ ٱلَّذِي كَانُواْ يُوعَدُونَ
Ojú wọn yóò wálẹ̀. Ìyẹpẹrẹ máa bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ọjọ́ yẹn ni èyí tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
 
وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی المعارج
پێڕستی سوره‌ته‌كان ژمارەی پەڕە
 
وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

وەرگێڕاوی ماناکانی قورئانی پیرۆز بۆ زمانی یوربا، وەرگێڕان: شێخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني، چاپی ساڵی 1432ك.

داخستن