Bản dịch ý nghĩa nội dung Qur'an - Dịch thuật tiếng Yoruba * - Mục lục các bản dịch

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Ý nghĩa nội dung Chương: Chương Al-Ma-'arij   Câu:

Suuratul-Mahaarij

سَأَلَ سَآئِلُۢ بِعَذَابٖ وَاقِعٖ
Oníbèéèrè kan bèèrè nípa ìyà tó máa ṣẹlẹ̀
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
لِّلۡكَٰفِرِينَ لَيۡسَ لَهُۥ دَافِعٞ
sí àwọn aláìgbàgbọ́. Kò sì sí ẹni tí ó máa dí i lọ́wọ́
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
مِّنَ ٱللَّهِ ذِي ٱلۡمَعَارِجِ
lọ́dọ̀ Allāhu, Onípò-àyè gíga.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
تَعۡرُجُ ٱلۡمَلَٰٓئِكَةُ وَٱلرُّوحُ إِلَيۡهِ فِي يَوۡمٖ كَانَ مِقۡدَارُهُۥ خَمۡسِينَ أَلۡفَ سَنَةٖ
Àwọn mọlāika àti mọlāika Jibrīl ń gùnkè wá sí ọ̀dọ̀ Rẹ̀ nínú ọjọ́ kan tí òdiwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún (tí ẹ bá fẹ́ rìn ín).¹
1. Ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún ni ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta ọdún (50,000). Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Hajj; 22:47.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
فَٱصۡبِرۡ صَبۡرٗا جَمِيلًا
Nítorí náà, ṣe sùúrù ní sùúrù tó rẹwà.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
إِنَّهُمۡ يَرَوۡنَهُۥ بَعِيدٗا
Dájúdájú wọ́n ń wo (ìyà náà) ní ohun tó jìnnà.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَنَرَىٰهُ قَرِيبٗا
A sì ń wò ó ní ohun tó súnmọ́.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
يَوۡمَ تَكُونُ ٱلسَّمَآءُ كَٱلۡمُهۡلِ
(Ọjọ́ náà ni) ọjọ́ tí sánmọ̀ yó dà bí ògéré epo gbígbóná,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَتَكُونُ ٱلۡجِبَالُ كَٱلۡعِهۡنِ
àwọn àpáta yó sì dà bí ẹ̀gbọ̀n òwú-irun,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَلَا يَسۡـَٔلُ حَمِيمٌ حَمِيمٗا
ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ kan kò sì níí bèèrè ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ (rẹ̀).
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
يُبَصَّرُونَهُمۡۚ يَوَدُّ ٱلۡمُجۡرِمُ لَوۡ يَفۡتَدِي مِنۡ عَذَابِ يَوۡمِئِذِۭ بِبَنِيهِ
Wọ́n máa rí ara wọn (wọ́n sì máa dára wọn mọ̀). Ẹlẹ́ṣẹ̀ sì máa fẹ́ kí òun fi àwọn ọmọ rẹ̀ ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà ní ọjọ́ yẹn.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَصَٰحِبَتِهِۦ وَأَخِيهِ
Ìyàwó rẹ̀ àti arákùnrin rẹ̀,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَفَصِيلَتِهِ ٱلَّتِي تُـٔۡوِيهِ
àti àwọn ẹbí rẹ̀ tó pa tì, tí àwọn sì ń gbà á sọ́dọ̀ nílé ayé,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَمَن فِي ٱلۡأَرۡضِ جَمِيعٗا ثُمَّ يُنجِيهِ
àti gbogbo ẹni tó wà lórí ilẹ̀ ayé pátápátá, (ó máa fẹ́ fi wọ́n ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà). Lẹ́yìn náà, (ó máa fẹ́) kí Allāhu gba òun là (nínú ìyà Iná).
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
كَلَّآۖ إِنَّهَا لَظَىٰ
Rárá! Dájúdájú (ó máa wọ) iná Laṭḥọ̄ (iná tó ń jò fòfò).
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
نَزَّاعَةٗ لِّلشَّوَىٰ
Ó máa bó awọ orí tòró.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
تَدۡعُواْ مَنۡ أَدۡبَرَ وَتَوَلَّىٰ
(Iná) yó máa ké sí ẹni tó kẹ̀yìn sí (ìgbágbọ́ òdodo), tí ó sì takété sí i,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَجَمَعَ فَأَوۡعَىٰٓ
ó kó (ọrọ̀) jọ, ó sì fi pamọ́ (kò ná an fún ẹ̀sìn).
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
۞ إِنَّ ٱلۡإِنسَٰنَ خُلِقَ هَلُوعًا
Dájúdájú ènìyàn, A ṣẹ̀dá rẹ̀ ní aláìlọ́kàn, ọ̀kánjúà.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
إِذَا مَسَّهُ ٱلشَّرُّ جَزُوعٗا
Nígbà tí aburú bá fọwọ́ bà á, ó máa kanra gógó.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَإِذَا مَسَّهُ ٱلۡخَيۡرُ مَنُوعًا
Nígbà tí ọwọ́ rẹ̀ bá sì ba oore, ó máa yahun.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
إِلَّا ٱلۡمُصَلِّينَ
Àyàfi àwọn olùkírun,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
ٱلَّذِينَ هُمۡ عَلَىٰ صَلَاتِهِمۡ دَآئِمُونَ
àwọn tí wọ́n dúnnímọ́ ìrun wọn;
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَٱلَّذِينَ فِيٓ أَمۡوَٰلِهِمۡ حَقّٞ مَّعۡلُومٞ
àwọn tó mọ ojúṣe (wọn) nínú dúkìá wọn
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
لِّلسَّآئِلِ وَٱلۡمَحۡرُومِ
sí alágbe àti ẹni tí A ṣe arísìkí ní èèwọ̀ fún;
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَٱلَّذِينَ يُصَدِّقُونَ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
àwọn tó ń gba ọjọ́ ẹ̀san gbọ́ ní òdodo;
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَٱلَّذِينَ هُم مِّنۡ عَذَابِ رَبِّهِم مُّشۡفِقُونَ
àwọn tó ń páyà ìyà Olúwa wọn,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
إِنَّ عَذَابَ رَبِّهِمۡ غَيۡرُ مَأۡمُونٖ
dájúdájú ìyà Olúwa wọn kò ṣeé fàyàbalẹ̀ sí;
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ لِفُرُوجِهِمۡ حَٰفِظُونَ
àwọn tó ń ṣọ́ abẹ́ wọn,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
إِلَّا عَلَىٰٓ أَزۡوَٰجِهِمۡ أَوۡ مَا مَلَكَتۡ أَيۡمَٰنُهُمۡ فَإِنَّهُمۡ غَيۡرُ مَلُومِينَ
àyàfi lọ́dọ̀ àwọn ìyàwó wọn tàbí ẹrúbìnrin wọn ni wọn kò ti lè jẹ́ ẹni-èébú,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
فَمَنِ ٱبۡتَغَىٰ وَرَآءَ ذَٰلِكَ فَأُوْلَٰٓئِكَ هُمُ ٱلۡعَادُونَ
nítorí náà, ẹnikẹ́ni tó bá ń wá n̄ǹkan mìíràn lẹ́yìn ìyẹn, àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni olùtayọ-ẹnu ààlà;
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ لِأَمَٰنَٰتِهِمۡ وَعَهۡدِهِمۡ رَٰعُونَ
àwọn tó ń ṣọ́ àgbàfipamọ́ wọn àti àdéhùn wọn;
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَٱلَّذِينَ هُم بِشَهَٰدَٰتِهِمۡ قَآئِمُونَ
àwọn tó ń dúró ti ìjẹ́rìí (òdodo) wọn;
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
وَٱلَّذِينَ هُمۡ عَلَىٰ صَلَاتِهِمۡ يُحَافِظُونَ
àti àwọn tó ń ṣọ́ àwọn ìrun wọn.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
أُوْلَٰٓئِكَ فِي جَنَّٰتٖ مُّكۡرَمُونَ
Àwọn wọ̀nyẹn ni alápọ̀n-ọ́nlé nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
فَمَالِ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ قِبَلَكَ مُهۡطِعِينَ
Kí ló mú àwọn tí kò gbàgbọ́ tí ara wọn kò balẹ̀ níwájú rẹ,
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
عَنِ ٱلۡيَمِينِ وَعَنِ ٱلشِّمَالِ عِزِينَ
tí wọ́n sì jókòó ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí sí ọwọ́ ọ̀tún àti ọwọ́ òsì (rẹ)?
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
أَيَطۡمَعُ كُلُّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ أَن يُدۡخَلَ جَنَّةَ نَعِيمٖ
Ṣé ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń jẹ̀rankàn pé A óò mú òun wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra ni?
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
كَلَّآۖ إِنَّا خَلَقۡنَٰهُم مِّمَّا يَعۡلَمُونَ
Rárá o! Dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá wọn láti inú ohun tí wọ́n mọ̀.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
فَلَآ أُقۡسِمُ بِرَبِّ ٱلۡمَشَٰرِقِ وَٱلۡمَغَٰرِبِ إِنَّا لَقَٰدِرُونَ
Nítorí náà, Èmi ń fi Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn àti àwọn ibùwọ̀ òòrùn¹ búra, dájúdájú Àwa ni Alágbára
1. Ìyẹn ni pé, Èmi, Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn àti ibùwọ̀ òòrùn ń fi ara Mi búra. Wòóore: Èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣriƙ” àti “mọgrib” nínú sūrah al-Muzzammil; 73:9 ni agbègbè ibùyọ òòrùn àti agbègbè ibùwọ̀ òòrùn. Èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣriƙọen” nínú sūrah ar-Rahmọ̄n; 55:17 ni ibùyọ òòrùn lásìkò ẹ̀rùn àti ibùyọ òòrùn lásìkò òjò. Bákan náà, “mọgribaen” ibùwọ̀ òòrùn lásìkò ẹ̀rùn àti ibùwọ̀ òòrùn lásìkò òjò. Bákan náà, èròǹgbà Allāhu pẹ̀lú “mọṣāriƙ àti mọgārib” ni àwọn ọgọ́sàn-án ibùyọ òòrùn àti ọgọ́sàn-án ibùwọ̀ òòrùn. (Tafsīr Bagawiy)
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
عَلَىٰٓ أَن نُّبَدِّلَ خَيۡرٗا مِّنۡهُمۡ وَمَا نَحۡنُ بِمَسۡبُوقِينَ
láti yí (ìrísí wọn) padà (ní ọjọ́ Àjíǹde) sí (ìrísí kan) tó máa dára ju (ìrísí) wọn (tayé). Kò sì sí ẹni tó lè dá Wa lágara.¹
1. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Ƙiyāmọh; 75:3-4.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
فَذَرۡهُمۡ يَخُوضُواْ وَيَلۡعَبُواْ حَتَّىٰ يُلَٰقُواْ يَوۡمَهُمُ ٱلَّذِي يُوعَدُونَ
Nítorí náà, fi wọ́n sílẹ̀ kí wọ́n máa sọ ìsọkúsọ (wọn), kí wọ́n sì máa ṣeré títí wọn yóò fi pàdé ọjọ́ wọn tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
يَوۡمَ يَخۡرُجُونَ مِنَ ٱلۡأَجۡدَاثِ سِرَاعٗا كَأَنَّهُمۡ إِلَىٰ نُصُبٖ يُوفِضُونَ
Ọjọ́ tí wọn yóò sáré jáde wéréwéré láti inú àwọn sàréè, wọn yó sì dà bí ẹni pé wọ́n ń yára lọ sídìí ohun àfojúsùn kan.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
خَٰشِعَةً أَبۡصَٰرُهُمۡ تَرۡهَقُهُمۡ ذِلَّةٞۚ ذَٰلِكَ ٱلۡيَوۡمُ ٱلَّذِي كَانُواْ يُوعَدُونَ
Ojú wọn yóò wálẹ̀. Ìyẹpẹrẹ máa bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ọjọ́ yẹn ni èyí tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
 
Ý nghĩa nội dung Chương: Chương Al-Ma-'arij
Mục lục các chương Kinh Số trang
 
Bản dịch ý nghĩa nội dung Qur'an - Dịch thuật tiếng Yoruba - Mục lục các bản dịch

Bản dịch ý nghĩa nội dung Kinh Qur'an bằng tiếng Yoruba, dịch thuật bởi Sheikh Abu Rahimah Mika-il Ikweeni, xuất bản năm 1432 A.H

Đóng lại