Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation * - Translations’ Index

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Translation of the meanings Surah: Al-Fajr   Ayah:

Suuratul-Faj'r

وَٱلۡفَجۡرِ
Allāhu fi àfẹ̀mọ́júmọ́ búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَيَالٍ عَشۡرٖ
Ó tún fi àwọn òru mẹ́wàá kan búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱلشَّفۡعِ وَٱلۡوَتۡرِ
Ó tún fi n̄ǹkan tí eéjì ń pín geerege àti n̄ǹkan tí eéjì kò pín geerege búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱلَّيۡلِ إِذَا يَسۡرِ
Ó tún fi òru nígbà tí ó bá dé búra.
Arabic explanations of the Qur’an:
هَلۡ فِي ذَٰلِكَ قَسَمٞ لِّذِي حِجۡرٍ
Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?
Arabic explanations of the Qur’an:
أَلَمۡ تَرَ كَيۡفَ فَعَلَ رَبُّكَ بِعَادٍ
Ṣé o kò wòye sí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,
Arabic explanations of the Qur’an:
إِرَمَ ذَاتِ ٱلۡعِمَادِ
(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱلَّتِي لَمۡ يُخۡلَقۡ مِثۡلُهَا فِي ٱلۡبِلَٰدِ
àwọn tí A kò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?
Arabic explanations of the Qur’an:
وَثَمُودَ ٱلَّذِينَ جَابُواْ ٱلصَّخۡرَ بِٱلۡوَادِ
Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonúfojì,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَفِرۡعَوۡنَ ذِي ٱلۡأَوۡتَادِ
àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱلَّذِينَ طَغَوۡاْ فِي ٱلۡبِلَٰدِ
(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn tó tayọ ẹnu-ààlà nínú ìlú.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَأَكۡثَرُواْ فِيهَا ٱلۡفَسَادَ
Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَصَبَّ عَلَيۡهِمۡ رَبُّكَ سَوۡطَ عَذَابٍ
Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.
Arabic explanations of the Qur’an:
إِنَّ رَبَّكَ لَبِٱلۡمِرۡصَادِ
Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).
Arabic explanations of the Qur’an:
فَأَمَّا ٱلۡإِنسَٰنُ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ رَبُّهُۥ فَأَكۡرَمَهُۥ وَنَعَّمَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَكۡرَمَنِ
Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti pọ́n mi lé.”
Arabic explanations of the Qur’an:
وَأَمَّآ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ فَقَدَرَ عَلَيۡهِ رِزۡقَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَهَٰنَنِ
Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi.”
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّاۖ بَل لَّا تُكۡرِمُونَ ٱلۡيَتِيمَ
Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَا تَحَٰٓضُّونَ عَلَىٰ طَعَامِ ٱلۡمِسۡكِينِ
Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَتَأۡكُلُونَ ٱلتُّرَاثَ أَكۡلٗا لَّمّٗا
Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَتُحِبُّونَ ٱلۡمَالَ حُبّٗا جَمّٗا
Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.
Arabic explanations of the Qur’an:
كَلَّآۖ إِذَا دُكَّتِ ٱلۡأَرۡضُ دَكّٗا دَكّٗا
Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (tó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),
Arabic explanations of the Qur’an:
وَجَآءَ رَبُّكَ وَٱلۡمَلَكُ صَفّٗا صَفّٗا
(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,
Arabic explanations of the Qur’an:
وَجِاْيٓءَ يَوۡمَئِذِۭ بِجَهَنَّمَۚ يَوۡمَئِذٖ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ وَأَنَّىٰ لَهُ ٱلذِّكۡرَىٰ
ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!
Arabic explanations of the Qur’an:
يَقُولُ يَٰلَيۡتَنِي قَدَّمۡتُ لِحَيَاتِي
Ó máa wí pé: “Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi.”
Arabic explanations of the Qur’an:
فَيَوۡمَئِذٖ لَّا يُعَذِّبُ عَذَابَهُۥٓ أَحَدٞ
Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).
Arabic explanations of the Qur’an:
وَلَا يُوثِقُ وَثَاقَهُۥٓ أَحَدٞ
Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).
Arabic explanations of the Qur’an:
يَٰٓأَيَّتُهَا ٱلنَّفۡسُ ٱلۡمُطۡمَئِنَّةُ
Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,
Arabic explanations of the Qur’an:
ٱرۡجِعِيٓ إِلَىٰ رَبِّكِ رَاضِيَةٗ مَّرۡضِيَّةٗ
padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.
Arabic explanations of the Qur’an:
فَٱدۡخُلِي فِي عِبَٰدِي
Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.
Arabic explanations of the Qur’an:
وَٱدۡخُلِي جَنَّتِي
Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.
Arabic explanations of the Qur’an:
 
Translation of the meanings Surah: Al-Fajr
Surahs’ Index Page Number
 
Translation of the Meanings of the Noble Qur'an - Yoruba translation - Translations’ Index

Translation of the Quran meanings into Yoruba by Abu Rahima Mikhail Aikweiny, printed in 1432 H.

close