Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Capítulo: Sura Al-Qiyaama   Versículo:

Suuratul-Qiyaamah

لَآ أُقۡسِمُ بِيَوۡمِ ٱلۡقِيَٰمَةِ
Èmi (Allāhu) ń fi Ọjọ́ Àjíǹde búra.
Las Exégesis Árabes:
وَلَآ أُقۡسِمُ بِٱلنَّفۡسِ ٱللَّوَّامَةِ
Mo tún ń fi ẹ̀mí tó máa dá ara rẹ̀ ní ẹ̀bi búra.
Las Exégesis Árabes:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَلَّن نَّجۡمَعَ عِظَامَهُۥ
Ṣé ènìyàn lérò pé A kò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
Las Exégesis Árabes:
بَلَىٰ قَٰدِرِينَ عَلَىٰٓ أَن نُّسَوِّيَ بَنَانَهُۥ
Rárá. (À ń jẹ́) Alágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.
1.Àwọn ọmọníka ọwọ́ àti ọmọníka ẹsẹ̀, ọ̀tún rẹ̀ àti òsì rẹ̀. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Mọ̄‘rij; 70:40-41.
Las Exégesis Árabes:
بَلۡ يُرِيدُ ٱلۡإِنسَٰنُ لِيَفۡجُرَ أَمَامَهُۥ
Rárá ènìyàn fẹ́ máa ṣe aburú lọ bẹ́ẹ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀
Las Exégesis Árabes:
يَسۡـَٔلُ أَيَّانَ يَوۡمُ ٱلۡقِيَٰمَةِ
ni ó fi ń bèèrè pé: “Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?”
Las Exégesis Árabes:
فَإِذَا بَرِقَ ٱلۡبَصَرُ
Nígbà tí ojú bá rí ìdààmú tó sì yà sílẹ̀ tí kò lè padé,
Las Exégesis Árabes:
وَخَسَفَ ٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
Las Exégesis Árabes:
وَجُمِعَ ٱلشَّمۡسُ وَٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí wọ́n bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn tí ìmọ́lẹ̀ méjèèjì pòóró,
Las Exégesis Árabes:
يَقُولُ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذٍ أَيۡنَ ٱلۡمَفَرُّ
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: “Níbo ni ibùsásí wà?”
Las Exégesis Árabes:
كَلَّا لَا وَزَرَ
Rárá, kò sí ibùsásí.
Las Exégesis Árabes:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمُسۡتَقَرُّ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
Las Exégesis Árabes:
يُنَبَّؤُاْ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذِۭ بِمَا قَدَّمَ وَأَخَّرَ
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun tó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
Las Exégesis Árabes:
بَلِ ٱلۡإِنسَٰنُ عَلَىٰ نَفۡسِهِۦ بَصِيرَةٞ
Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,
Las Exégesis Árabes:
وَلَوۡ أَلۡقَىٰ مَعَاذِيرَهُۥ
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
Las Exégesis Árabes:
لَا تُحَرِّكۡ بِهِۦ لِسَانَكَ لِتَعۡجَلَ بِهِۦٓ
Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّ عَلَيۡنَا جَمۡعَهُۥ وَقُرۡءَانَهُۥ
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
فَإِذَا قَرَأۡنَٰهُ فَٱتَّبِعۡ قُرۡءَانَهُۥ
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ إِنَّ عَلَيۡنَا بَيَانَهُۥ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
Las Exégesis Árabes:
كَلَّا بَلۡ تُحِبُّونَ ٱلۡعَاجِلَةَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé ni.
Las Exégesis Árabes:
وَتَذَرُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Ẹ sì ń gbé ọ̀run jù sílẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ نَّاضِرَةٌ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
Las Exégesis Árabes:
إِلَىٰ رَبِّهَا نَاظِرَةٞ
Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.
Las Exégesis Árabes:
وَوُجُوهٞ يَوۡمَئِذِۭ بَاسِرَةٞ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
Las Exégesis Árabes:
تَظُنُّ أَن يُفۡعَلَ بِهَا فَاقِرَةٞ
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé wọ́n máa fi aburú kan òhun.
Las Exégesis Árabes:
كَلَّآ إِذَا بَلَغَتِ ٱلتَّرَاقِيَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
Las Exégesis Árabes:
وَقِيلَ مَنۡۜ رَاقٖ
A sì máa sọ pé: “Ǹjẹ́ olùpọfọ̀ kan wà bí (tí ó máa pọfọ̀ láti gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
Las Exégesis Árabes:
وَظَنَّ أَنَّهُ ٱلۡفِرَاقُ
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلۡتَفَّتِ ٱلسَّاقُ بِٱلسَّاقِ
Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.
Las Exégesis Árabes:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمَسَاقُ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
Las Exégesis Árabes:
فَلَا صَدَّقَ وَلَا صَلَّىٰ
Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.
Las Exégesis Árabes:
وَلَٰكِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰ
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo ní irọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ ذَهَبَ إِلَىٰٓ أَهۡلِهِۦ يَتَمَطَّىٰٓ
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
Las Exégesis Árabes:
أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰ
(Ìparun nílé ayé) ló tọ́ sí ọ jùlọ (lórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ wọ̀nyẹn). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰٓ
Lẹ́yìn náà, (Iná) ló tọ́ sí ọ jùlọ (ní ọ̀run). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
Las Exégesis Árabes:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَن يُتۡرَكَ سُدًى
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
Las Exégesis Árabes:
أَلَمۡ يَكُ نُطۡفَةٗ مِّن مَّنِيّٖ يُمۡنَىٰ
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ كَانَ عَلَقَةٗ فَخَلَقَ فَسَوَّىٰ
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é tó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
Las Exégesis Árabes:
فَجَعَلَ مِنۡهُ ٱلزَّوۡجَيۡنِ ٱلذَّكَرَ وَٱلۡأُنثَىٰٓ
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti ara rẹ̀, akọ àti abo.
Las Exégesis Árabes:
أَلَيۡسَ ذَٰلِكَ بِقَٰدِرٍ عَلَىٰٓ أَن يُحۡـِۧيَ ٱلۡمَوۡتَىٰ
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Capítulo: Sura Al-Qiyaama
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar