Check out the new design

Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Abu Rahima Mikael * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Capítulo: An-Naba   Versículo:

An-Naba'

عَمَّ يَتَسَآءَلُونَ
Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
Las Exégesis Árabes:
عَنِ ٱلنَّبَإِ ٱلۡعَظِيمِ
Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
Las Exégesis Árabes:
ٱلَّذِي هُمۡ فِيهِ مُخۡتَلِفُونَ
èyí tí wọ́n ń yapa-ẹnu lórí rẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ كَلَّا سَيَعۡلَمُونَ
Lẹ́yìn náà, rárá sẹ́, wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
Las Exégesis Árabes:
أَلَمۡ نَجۡعَلِ ٱلۡأَرۡضَ مِهَٰدٗا
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
Las Exégesis Árabes:
وَٱلۡجِبَالَ أَوۡتَادٗا
àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
Las Exégesis Árabes:
وَخَلَقۡنَٰكُمۡ أَزۡوَٰجٗا
A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
Las Exégesis Árabes:
وَجَعَلۡنَا نَوۡمَكُمۡ سُبَاتٗا
A ṣe oorun yín ní ìsinmi.
Las Exégesis Árabes:
وَجَعَلۡنَا ٱلَّيۡلَ لِبَاسٗا
A tún ṣe alẹ́ ní ìbora.
Las Exégesis Árabes:
وَجَعَلۡنَا ٱلنَّهَارَ مَعَاشٗا
A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
Las Exégesis Árabes:
وَبَنَيۡنَا فَوۡقَكُمۡ سَبۡعٗا شِدَادٗا
A tún mọ sánmọ̀ méje tó lágbára sókè yín.
Las Exégesis Árabes:
وَجَعَلۡنَا سِرَاجٗا وَهَّاجٗا
A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ tó ń tàn gbòlà.
Las Exégesis Árabes:
وَأَنزَلۡنَا مِنَ ٱلۡمُعۡصِرَٰتِ مَآءٗ ثَجَّاجٗا
Àti pé A sọ omi tó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
Las Exégesis Árabes:
لِّنُخۡرِجَ بِهِۦ حَبّٗا وَنَبَاتٗا
nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
Las Exégesis Árabes:
وَجَنَّٰتٍ أَلۡفَافًا
pẹ̀lú àwọn ọgbà tó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّ يَوۡمَ ٱلۡفَصۡلِ كَانَ مِيقَٰتٗا
Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
Las Exégesis Árabes:
يَوۡمَ يُنفَخُ فِي ٱلصُّورِ فَتَأۡتُونَ أَفۡوَاجٗا
(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
Las Exégesis Árabes:
وَفُتِحَتِ ٱلسَّمَآءُ فَكَانَتۡ أَبۡوَٰبٗا
Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
Las Exégesis Árabes:
وَسُيِّرَتِ ٱلۡجِبَالُ فَكَانَتۡ سَرَابًا
Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّ جَهَنَّمَ كَانَتۡ مِرۡصَادٗا
Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
Las Exégesis Árabes:
لِّلطَّٰغِينَ مَـَٔابٗا
(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
Las Exégesis Árabes:
لَّٰبِثِينَ فِيهَآ أَحۡقَابٗا
Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
Las Exégesis Árabes:
لَّا يَذُوقُونَ فِيهَا بَرۡدٗا وَلَا شَرَابًا
Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
Las Exégesis Árabes:
إِلَّا حَمِيمٗا وَغَسَّاقٗا
àyàfi omi tó gbóná parí àti àwọnúwẹ̀jẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
جَزَآءٗ وِفَاقًا
(Ó jẹ́) ẹ̀san tó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
Las Exégesis Árabes:
إِنَّهُمۡ كَانُواْ لَا يَرۡجُونَ حِسَابٗا
Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
Las Exégesis Árabes:
وَكَذَّبُواْ بِـَٔايَٰتِنَا كِذَّابٗا
Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa ní irọ́ gan-an.
Las Exégesis Árabes:
وَكُلَّ شَيۡءٍ أَحۡصَيۡنَٰهُ كِتَٰبٗا
Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
Las Exégesis Árabes:
فَذُوقُواْ فَلَن نَّزِيدَكُمۡ إِلَّا عَذَابًا
Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fún yín bí kò ṣe ìyà.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Capítulo: An-Naba
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Abu Rahima Mikael - Índice de traducciones

Traducida por Sheij Abu Rahima Michael Aikueyeni.

Cerrar