Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba * - Índice de traducciones

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traducción de significados Capítulo: Sura An-Naazi'aat   Versículo:

Suuratun-Naazihaat

وَٱلنَّٰزِعَٰتِ غَرۡقٗا
Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلنَّٰشِطَٰتِ نَشۡطٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلسَّٰبِحَٰتِ سَبۡحٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.
Las Exégesis Árabes:
فَٱلسَّٰبِقَٰتِ سَبۡقٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.
Las Exégesis Árabes:
فَٱلۡمُدَبِّرَٰتِ أَمۡرٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.
Las Exégesis Árabes:
يَوۡمَ تَرۡجُفُ ٱلرَّاجِفَةُ
Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
Las Exégesis Árabes:
تَتۡبَعُهَا ٱلرَّادِفَةُ
Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn ìkejì fún àjíǹde máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
Las Exégesis Árabes:
قُلُوبٞ يَوۡمَئِذٖ وَاجِفَةٌ
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
Las Exégesis Árabes:
أَبۡصَٰرُهَا خَٰشِعَةٞ
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
Las Exégesis Árabes:
يَقُولُونَ أَءِنَّا لَمَرۡدُودُونَ فِي ٱلۡحَافِرَةِ
Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
Las Exégesis Árabes:
أَءِذَا كُنَّا عِظَٰمٗا نَّخِرَةٗ
Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”
Las Exégesis Árabes:
قَالُواْ تِلۡكَ إِذٗا كَرَّةٌ خَاسِرَةٞ
Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”
Las Exégesis Árabes:
فَإِنَّمَا هِيَ زَجۡرَةٞ وَٰحِدَةٞ
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
Las Exégesis Árabes:
فَإِذَا هُم بِٱلسَّاهِرَةِ
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
Las Exégesis Árabes:
هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ مُوسَىٰٓ
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
Las Exégesis Árabes:
إِذۡ نَادَىٰهُ رَبُّهُۥ بِٱلۡوَادِ ٱلۡمُقَدَّسِ طُوًى
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.
Las Exégesis Árabes:
ٱذۡهَبۡ إِلَىٰ فِرۡعَوۡنَ إِنَّهُۥ طَغَىٰ
Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.
Las Exégesis Árabes:
فَقُلۡ هَل لَّكَ إِلَىٰٓ أَن تَزَكَّىٰ
Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
Las Exégesis Árabes:
وَأَهۡدِيَكَ إِلَىٰ رَبِّكَ فَتَخۡشَىٰ
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”
Las Exégesis Árabes:
فَأَرَىٰهُ ٱلۡأٓيَةَ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.
Las Exégesis Árabes:
فَكَذَّبَ وَعَصَىٰ
(Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).
Las Exégesis Árabes:
ثُمَّ أَدۡبَرَ يَسۡعَىٰ
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
Las Exégesis Árabes:
فَحَشَرَ فَنَادَىٰ
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
Las Exégesis Árabes:
فَقَالَ أَنَا۠ رَبُّكُمُ ٱلۡأَعۡلَىٰ
Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”
Las Exégesis Árabes:
فَأَخَذَهُ ٱللَّهُ نَكَالَ ٱلۡأٓخِرَةِ وَٱلۡأُولَىٰٓ
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).¹
1. Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: “Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!” Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
Las Exégesis Árabes:
إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَعِبۡرَةٗ لِّمَن يَخۡشَىٰٓ
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).
Las Exégesis Árabes:
ءَأَنتُمۡ أَشَدُّ خَلۡقًا أَمِ ٱلسَّمَآءُۚ بَنَىٰهَا
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
Las Exégesis Árabes:
رَفَعَ سَمۡكَهَا فَسَوَّىٰهَا
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.
Las Exégesis Árabes:
وَأَغۡطَشَ لَيۡلَهَا وَأَخۡرَجَ ضُحَىٰهَا
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلۡأَرۡضَ بَعۡدَ ذَٰلِكَ دَحَىٰهَآ
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
Las Exégesis Árabes:
أَخۡرَجَ مِنۡهَا مَآءَهَا وَمَرۡعَىٰهَا
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
وَٱلۡجِبَالَ أَرۡسَىٰهَا
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
Las Exégesis Árabes:
مَتَٰعٗا لَّكُمۡ وَلِأَنۡعَٰمِكُمۡ
Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
Las Exégesis Árabes:
فَإِذَا جَآءَتِ ٱلطَّآمَّةُ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
Las Exégesis Árabes:
يَوۡمَ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ مَا سَعَىٰ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.
Las Exégesis Árabes:
وَبُرِّزَتِ ٱلۡجَحِيمُ لِمَن يَرَىٰ
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.
Las Exégesis Árabes:
فَأَمَّا مَن طَغَىٰ
Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,
Las Exégesis Árabes:
وَءَاثَرَ ٱلۡحَيَوٰةَ ٱلدُّنۡيَا
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
Las Exégesis Árabes:
فَإِنَّ ٱلۡجَحِيمَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Las Exégesis Árabes:
وَأَمَّا مَنۡ خَافَ مَقَامَ رَبِّهِۦ وَنَهَى ٱلنَّفۡسَ عَنِ ٱلۡهَوَىٰ
Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
Las Exégesis Árabes:
فَإِنَّ ٱلۡجَنَّةَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Las Exégesis Árabes:
يَسۡـَٔلُونَكَ عَنِ ٱلسَّاعَةِ أَيَّانَ مُرۡسَىٰهَا
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”
Las Exégesis Árabes:
فِيمَ أَنتَ مِن ذِكۡرَىٰهَآ
Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?¹
1. Ìyẹn ni pé, ìwọ kò lè ní ìmọ̀ ọjọ́ rẹ̀. Ìmọ̀ nípa ọjọ́ wo gan-an ni òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ ni kò sí ìmọ̀ rẹ̀ ní ọ̀dọ̀ Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - àti gbogbo ẹ̀dá pátápátá. Ọ̀dọ̀ Allāhu nìkan ṣoṣo ni ìmọ̀ rẹ̀ wà. Àmọ́ Allāhu fi àwọn àmì ìṣáájú ọjọ́ náà mọ Ànábì Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, ìyẹn ni àwọn àmì òpin ayé.
Las Exégesis Árabes:
إِلَىٰ رَبِّكَ مُنتَهَىٰهَآ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
Las Exégesis Árabes:
إِنَّمَآ أَنتَ مُنذِرُ مَن يَخۡشَىٰهَا
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.
Las Exégesis Árabes:
كَأَنَّهُمۡ يَوۡمَ يَرَوۡنَهَا لَمۡ يَلۡبَثُوٓاْ إِلَّا عَشِيَّةً أَوۡ ضُحَىٰهَا
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.
Las Exégesis Árabes:
 
Traducción de significados Capítulo: Sura An-Naazi'aat
Índice de Capítulos Número de página
 
Traducción de los significados del Sagrado Corán - Traducción Yoruba - Índice de traducciones

Traducción de los significados del Sagrado Corán al idioma Yoruba por Abu Rahima Mikael Aikweiny. Año de impresión: 1432H.

Cerrar