Terjemahan makna Alquran Alkarim - Terjemahan Berbahasa Yoruba * - Daftar isi terjemahan

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Terjemahan makna Surah: Surah An-Nāzi'āt   Ayah:

Suuratun-Naazihaat

وَٱلنَّٰزِعَٰتِ غَرۡقٗا
Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.
Tafsir berbahasa Arab:
وَٱلنَّٰشِطَٰتِ نَشۡطٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.
Tafsir berbahasa Arab:
وَٱلسَّٰبِحَٰتِ سَبۡحٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.
Tafsir berbahasa Arab:
فَٱلسَّٰبِقَٰتِ سَبۡقٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.
Tafsir berbahasa Arab:
فَٱلۡمُدَبِّرَٰتِ أَمۡرٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.
Tafsir berbahasa Arab:
يَوۡمَ تَرۡجُفُ ٱلرَّاجِفَةُ
Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
Tafsir berbahasa Arab:
تَتۡبَعُهَا ٱلرَّادِفَةُ
Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn ìkejì fún àjíǹde máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
Tafsir berbahasa Arab:
قُلُوبٞ يَوۡمَئِذٖ وَاجِفَةٌ
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
Tafsir berbahasa Arab:
أَبۡصَٰرُهَا خَٰشِعَةٞ
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
Tafsir berbahasa Arab:
يَقُولُونَ أَءِنَّا لَمَرۡدُودُونَ فِي ٱلۡحَافِرَةِ
Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
Tafsir berbahasa Arab:
أَءِذَا كُنَّا عِظَٰمٗا نَّخِرَةٗ
Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”
Tafsir berbahasa Arab:
قَالُواْ تِلۡكَ إِذٗا كَرَّةٌ خَاسِرَةٞ
Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”
Tafsir berbahasa Arab:
فَإِنَّمَا هِيَ زَجۡرَةٞ وَٰحِدَةٞ
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
Tafsir berbahasa Arab:
فَإِذَا هُم بِٱلسَّاهِرَةِ
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
Tafsir berbahasa Arab:
هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ مُوسَىٰٓ
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
Tafsir berbahasa Arab:
إِذۡ نَادَىٰهُ رَبُّهُۥ بِٱلۡوَادِ ٱلۡمُقَدَّسِ طُوًى
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.
Tafsir berbahasa Arab:
ٱذۡهَبۡ إِلَىٰ فِرۡعَوۡنَ إِنَّهُۥ طَغَىٰ
Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.
Tafsir berbahasa Arab:
فَقُلۡ هَل لَّكَ إِلَىٰٓ أَن تَزَكَّىٰ
Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
Tafsir berbahasa Arab:
وَأَهۡدِيَكَ إِلَىٰ رَبِّكَ فَتَخۡشَىٰ
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”
Tafsir berbahasa Arab:
فَأَرَىٰهُ ٱلۡأٓيَةَ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.
Tafsir berbahasa Arab:
فَكَذَّبَ وَعَصَىٰ
(Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).
Tafsir berbahasa Arab:
ثُمَّ أَدۡبَرَ يَسۡعَىٰ
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
Tafsir berbahasa Arab:
فَحَشَرَ فَنَادَىٰ
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
Tafsir berbahasa Arab:
فَقَالَ أَنَا۠ رَبُّكُمُ ٱلۡأَعۡلَىٰ
Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”
Tafsir berbahasa Arab:
فَأَخَذَهُ ٱللَّهُ نَكَالَ ٱلۡأٓخِرَةِ وَٱلۡأُولَىٰٓ
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).¹
1. Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: “Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!” Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
Tafsir berbahasa Arab:
إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَعِبۡرَةٗ لِّمَن يَخۡشَىٰٓ
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).
Tafsir berbahasa Arab:
ءَأَنتُمۡ أَشَدُّ خَلۡقًا أَمِ ٱلسَّمَآءُۚ بَنَىٰهَا
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
Tafsir berbahasa Arab:
رَفَعَ سَمۡكَهَا فَسَوَّىٰهَا
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.
Tafsir berbahasa Arab:
وَأَغۡطَشَ لَيۡلَهَا وَأَخۡرَجَ ضُحَىٰهَا
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
Tafsir berbahasa Arab:
وَٱلۡأَرۡضَ بَعۡدَ ذَٰلِكَ دَحَىٰهَآ
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
Tafsir berbahasa Arab:
أَخۡرَجَ مِنۡهَا مَآءَهَا وَمَرۡعَىٰهَا
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
Tafsir berbahasa Arab:
وَٱلۡجِبَالَ أَرۡسَىٰهَا
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
Tafsir berbahasa Arab:
مَتَٰعٗا لَّكُمۡ وَلِأَنۡعَٰمِكُمۡ
Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
Tafsir berbahasa Arab:
فَإِذَا جَآءَتِ ٱلطَّآمَّةُ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
Tafsir berbahasa Arab:
يَوۡمَ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ مَا سَعَىٰ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.
Tafsir berbahasa Arab:
وَبُرِّزَتِ ٱلۡجَحِيمُ لِمَن يَرَىٰ
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.
Tafsir berbahasa Arab:
فَأَمَّا مَن طَغَىٰ
Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,
Tafsir berbahasa Arab:
وَءَاثَرَ ٱلۡحَيَوٰةَ ٱلدُّنۡيَا
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
Tafsir berbahasa Arab:
فَإِنَّ ٱلۡجَحِيمَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Tafsir berbahasa Arab:
وَأَمَّا مَنۡ خَافَ مَقَامَ رَبِّهِۦ وَنَهَى ٱلنَّفۡسَ عَنِ ٱلۡهَوَىٰ
Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
Tafsir berbahasa Arab:
فَإِنَّ ٱلۡجَنَّةَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Tafsir berbahasa Arab:
يَسۡـَٔلُونَكَ عَنِ ٱلسَّاعَةِ أَيَّانَ مُرۡسَىٰهَا
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”
Tafsir berbahasa Arab:
فِيمَ أَنتَ مِن ذِكۡرَىٰهَآ
Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?¹
1. Ìyẹn ni pé, ìwọ kò lè ní ìmọ̀ ọjọ́ rẹ̀. Ìmọ̀ nípa ọjọ́ wo gan-an ni òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ ni kò sí ìmọ̀ rẹ̀ ní ọ̀dọ̀ Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - àti gbogbo ẹ̀dá pátápátá. Ọ̀dọ̀ Allāhu nìkan ṣoṣo ni ìmọ̀ rẹ̀ wà. Àmọ́ Allāhu fi àwọn àmì ìṣáájú ọjọ́ náà mọ Ànábì Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, ìyẹn ni àwọn àmì òpin ayé.
Tafsir berbahasa Arab:
إِلَىٰ رَبِّكَ مُنتَهَىٰهَآ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
Tafsir berbahasa Arab:
إِنَّمَآ أَنتَ مُنذِرُ مَن يَخۡشَىٰهَا
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.
Tafsir berbahasa Arab:
كَأَنَّهُمۡ يَوۡمَ يَرَوۡنَهَا لَمۡ يَلۡبَثُوٓاْ إِلَّا عَشِيَّةً أَوۡ ضُحَىٰهَا
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.
Tafsir berbahasa Arab:
 
Terjemahan makna Surah: Surah An-Nāzi'āt
Daftar surah Nomor Halaman
 
Terjemahan makna Alquran Alkarim - Terjemahan Berbahasa Yoruba - Daftar isi terjemahan

Terjemahan makna Al-Qur`ān Al-Karīm ke bahasa Yoruba oleh Syekh Abu Rahimah Mikael Aykoyini. Cetakan tahun 1432 H.

Tutup