وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی * - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی النازعات   ئایه‌تی:

Suuratun-Naazihaat

وَٱلنَّٰزِعَٰتِ غَرۡقٗا
Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلنَّٰشِطَٰتِ نَشۡطٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلسَّٰبِحَٰتِ سَبۡحٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَٱلسَّٰبِقَٰتِ سَبۡقٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَٱلۡمُدَبِّرَٰتِ أَمۡرٗا
Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
يَوۡمَ تَرۡجُفُ ٱلرَّاجِفَةُ
Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
تَتۡبَعُهَا ٱلرَّادِفَةُ
Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.¹
1. Ìyẹn ní ọjọ́ tí ìfọn ìkejì fún àjíǹde máa ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú ohùn igbe tó máa le pin.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
قُلُوبٞ يَوۡمَئِذٖ وَاجِفَةٌ
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
أَبۡصَٰرُهَا خَٰشِعَةٞ
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
يَقُولُونَ أَءِنَّا لَمَرۡدُودُونَ فِي ٱلۡحَافِرَةِ
Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
أَءِذَا كُنَّا عِظَٰمٗا نَّخِرَةٗ
Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
قَالُواْ تِلۡكَ إِذٗا كَرَّةٌ خَاسِرَةٞ
Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَإِنَّمَا هِيَ زَجۡرَةٞ وَٰحِدَةٞ
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَإِذَا هُم بِٱلسَّاهِرَةِ
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ مُوسَىٰٓ
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِذۡ نَادَىٰهُ رَبُّهُۥ بِٱلۡوَادِ ٱلۡمُقَدَّسِ طُوًى
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ٱذۡهَبۡ إِلَىٰ فِرۡعَوۡنَ إِنَّهُۥ طَغَىٰ
Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَقُلۡ هَل لَّكَ إِلَىٰٓ أَن تَزَكَّىٰ
Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَأَهۡدِيَكَ إِلَىٰ رَبِّكَ فَتَخۡشَىٰ
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَأَرَىٰهُ ٱلۡأٓيَةَ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَكَذَّبَ وَعَصَىٰ
(Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ثُمَّ أَدۡبَرَ يَسۡعَىٰ
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَحَشَرَ فَنَادَىٰ
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَقَالَ أَنَا۠ رَبُّكُمُ ٱلۡأَعۡلَىٰ
Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَأَخَذَهُ ٱللَّهُ نَكَالَ ٱلۡأٓخِرَةِ وَٱلۡأُولَىٰٓ
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).¹
1. Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: “Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!” Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَعِبۡرَةٗ لِّمَن يَخۡشَىٰٓ
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
ءَأَنتُمۡ أَشَدُّ خَلۡقًا أَمِ ٱلسَّمَآءُۚ بَنَىٰهَا
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
تەفسیرە عەرەبیەکان:
رَفَعَ سَمۡكَهَا فَسَوَّىٰهَا
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَأَغۡطَشَ لَيۡلَهَا وَأَخۡرَجَ ضُحَىٰهَا
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلۡأَرۡضَ بَعۡدَ ذَٰلِكَ دَحَىٰهَآ
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.¹
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
أَخۡرَجَ مِنۡهَا مَآءَهَا وَمَرۡعَىٰهَا
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَٱلۡجِبَالَ أَرۡسَىٰهَا
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
مَتَٰعٗا لَّكُمۡ وَلِأَنۡعَٰمِكُمۡ
Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَإِذَا جَآءَتِ ٱلطَّآمَّةُ ٱلۡكُبۡرَىٰ
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
يَوۡمَ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ مَا سَعَىٰ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَبُرِّزَتِ ٱلۡجَحِيمُ لِمَن يَرَىٰ
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَأَمَّا مَن طَغَىٰ
Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَءَاثَرَ ٱلۡحَيَوٰةَ ٱلدُّنۡيَا
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَإِنَّ ٱلۡجَحِيمَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
وَأَمَّا مَنۡ خَافَ مَقَامَ رَبِّهِۦ وَنَهَى ٱلنَّفۡسَ عَنِ ٱلۡهَوَىٰ
Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فَإِنَّ ٱلۡجَنَّةَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
تەفسیرە عەرەبیەکان:
يَسۡـَٔلُونَكَ عَنِ ٱلسَّاعَةِ أَيَّانَ مُرۡسَىٰهَا
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”
تەفسیرە عەرەبیەکان:
فِيمَ أَنتَ مِن ذِكۡرَىٰهَآ
Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?¹
1. Ìyẹn ni pé, ìwọ kò lè ní ìmọ̀ ọjọ́ rẹ̀. Ìmọ̀ nípa ọjọ́ wo gan-an ni òpin ayé máa ṣẹlẹ̀ ni kò sí ìmọ̀ rẹ̀ ní ọ̀dọ̀ Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - àti gbogbo ẹ̀dá pátápátá. Ọ̀dọ̀ Allāhu nìkan ṣoṣo ni ìmọ̀ rẹ̀ wà. Àmọ́ Allāhu fi àwọn àmì ìṣáájú ọjọ́ náà mọ Ànábì Rẹ̀ - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, ìyẹn ni àwọn àmì òpin ayé.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِلَىٰ رَبِّكَ مُنتَهَىٰهَآ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
إِنَّمَآ أَنتَ مُنذِرُ مَن يَخۡشَىٰهَا
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
كَأَنَّهُمۡ يَوۡمَ يَرَوۡنَهَا لَمۡ يَلۡبَثُوٓاْ إِلَّا عَشِيَّةً أَوۡ ضُحَىٰهَا
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.
تەفسیرە عەرەبیەکان:
 
وه‌رگێڕانی ماناكان سوره‌تی: سورەتی النازعات
پێڕستی سوره‌ته‌كان ژمارەی پەڕە
 
وه‌رگێڕانی ماناكانی قورئانی پیرۆز - وەرگێڕاوی یورباوی - پێڕستی وه‌رگێڕاوه‌كان

وەرگێڕاوی ماناکانی قورئانی پیرۆز بۆ زمانی یوربا، وەرگێڕان: شێخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني، چاپی ساڵی 1432ك.

داخستن