Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Verset: (102) Sourate: AN-NISÂ’
وَإِذَا كُنتَ فِيهِمۡ فَأَقَمۡتَ لَهُمُ ٱلصَّلَوٰةَ فَلۡتَقُمۡ طَآئِفَةٞ مِّنۡهُم مَّعَكَ وَلۡيَأۡخُذُوٓاْ أَسۡلِحَتَهُمۡۖ فَإِذَا سَجَدُواْ فَلۡيَكُونُواْ مِن وَرَآئِكُمۡ وَلۡتَأۡتِ طَآئِفَةٌ أُخۡرَىٰ لَمۡ يُصَلُّواْ فَلۡيُصَلُّواْ مَعَكَ وَلۡيَأۡخُذُواْ حِذۡرَهُمۡ وَأَسۡلِحَتَهُمۡۗ وَدَّ ٱلَّذِينَ كَفَرُواْ لَوۡ تَغۡفُلُونَ عَنۡ أَسۡلِحَتِكُمۡ وَأَمۡتِعَتِكُمۡ فَيَمِيلُونَ عَلَيۡكُم مَّيۡلَةٗ وَٰحِدَةٗۚ وَلَا جُنَاحَ عَلَيۡكُمۡ إِن كَانَ بِكُمۡ أَذٗى مِّن مَّطَرٍ أَوۡ كُنتُم مَّرۡضَىٰٓ أَن تَضَعُوٓاْ أَسۡلِحَتَكُمۡۖ وَخُذُواْ حِذۡرَكُمۡۗ إِنَّ ٱللَّهَ أَعَدَّ لِلۡكَٰفِرِينَ عَذَابٗا مُّهِينٗا
Nígbà tí o bá wà láààrin wọn, gbé ìrun dúró fún wọn. Kí igun kan nínú wọn kírun pẹ̀lú rẹ, kí wọ́n mú n̄ǹkan ìjagun wọn lọ́wọ́. Nígbà tí wọ́n bá sì forí kanlẹ̀ (tí wọ́n parí ìrun), kí wọn bọ́ sẹ́yìn yín, kí igun mìíràn tí kò tí ì kírun wá kírun pẹ̀lú rẹ. Kí wọ́n mú ìṣọ́ra wọn¹ àti n̄ǹkan ìjagun wọn lọ́wọ́.² Àwọn tó ṣàì gbàgbọ́ fẹ́ kí ẹ gbàgbé àwọn n̄ǹkan ìjagun yín àti n̄ǹkan ìgbádùn yín (ẹrù oúnjẹ yín), kí wọ́n lè kọlù yín ní ẹ̀ẹ̀ kan náà. Kò sí ẹ̀ṣẹ̀ fún yín tí ó bá jẹ́ pé ìpalára kan ń bẹ fún yín látara òjò tàbí (pé) ẹ jẹ́ aláìsàn, pé kí ẹ fi n̄ǹkan ìjagun yín sílẹ̀ (lórí ìrun). Ẹ mú n̄ǹkan ìṣọ́ra yín lọ́wọ́. Dájúdájú Allāhu ti pèsè ìyà tí í yẹpẹrẹ ẹ̀dá sílẹ̀ de àwọn aláìgbàgbọ́.
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ āyah 71.
2. Àpèjúwe ìrun ojú ogun nínú āyah yìí nìyí: Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - máa kí rákáà ẹyọ kan parí fún igun àkọ́kọ́. Ó máa wà lórí ìjókòó rẹ̀ bẹ́ẹ̀ títí igun náà yóò fi kí rákáà ẹyọ kan tí ó ṣẹ́kù kún un. Olúkùlùkù wọn sì máa sálámọ̀ fúnra rẹ̀ ní ìparí rákáà kejì. Igun kejì tí wọ́n dúró sẹ́yìn wọn máa bọ́ síwájú lẹ́yìn Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -, igun àkọ́kọ́ tí rákáà méjì tirẹ̀ ti pé máa bọ́ sẹ́yìn wọn. Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - máa kí rákáà ẹyọ kan tirẹ̀ tó ṣẹ́kù fún igun kejì. Lẹ́yìn náà, igun kejì yìí náà yóò kí rákáà ẹyọ kan tí ó ṣẹ́kù kún un. Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - lè sálámọ̀ tirẹ̀ tàbí kí ó dúró dè wọ́n láti sálámọ̀ fún wọn. Báyẹn ni àpèjúwe ìrun Subh, Ṭḥuhr, ‘Asr àti ‘Iṣā’ lójú ogun.
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Verset: (102) Sourate: AN-NISÂ’
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture