Check out the new design

Traduzione dei Significati del Sacro Corano - Traduzione in yoruba - Abu Rahima Mikail * - Indice Traduzioni

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduzione dei significati Sura: Al-Fajr   Versetto:

Al-Faj'r

وَٱلۡفَجۡرِ
Allāhu fi àfẹ̀mọ́júmọ́ búra.
Esegesi in lingua araba:
وَلَيَالٍ عَشۡرٖ
Ó tún fi àwọn òru mẹ́wàá kan búra.
Esegesi in lingua araba:
وَٱلشَّفۡعِ وَٱلۡوَتۡرِ
Ó tún fi n̄ǹkan tí eéjì ń pín geerege àti n̄ǹkan tí eéjì kò pín geerege búra.
Esegesi in lingua araba:
وَٱلَّيۡلِ إِذَا يَسۡرِ
Ó tún fi òru nígbà tí ó bá dé búra.
Esegesi in lingua araba:
هَلۡ فِي ذَٰلِكَ قَسَمٞ لِّذِي حِجۡرٍ
Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?
Esegesi in lingua araba:
أَلَمۡ تَرَ كَيۡفَ فَعَلَ رَبُّكَ بِعَادٍ
Ṣé o kò wòye sí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,
Esegesi in lingua araba:
إِرَمَ ذَاتِ ٱلۡعِمَادِ
(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,
Esegesi in lingua araba:
ٱلَّتِي لَمۡ يُخۡلَقۡ مِثۡلُهَا فِي ٱلۡبِلَٰدِ
àwọn tí A kò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?
Esegesi in lingua araba:
وَثَمُودَ ٱلَّذِينَ جَابُواْ ٱلصَّخۡرَ بِٱلۡوَادِ
Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonúfojì,
Esegesi in lingua araba:
وَفِرۡعَوۡنَ ذِي ٱلۡأَوۡتَادِ
àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?
Esegesi in lingua araba:
ٱلَّذِينَ طَغَوۡاْ فِي ٱلۡبِلَٰدِ
(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn tó tayọ ẹnu-ààlà nínú ìlú.
Esegesi in lingua araba:
فَأَكۡثَرُواْ فِيهَا ٱلۡفَسَادَ
Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.
Esegesi in lingua araba:
فَصَبَّ عَلَيۡهِمۡ رَبُّكَ سَوۡطَ عَذَابٍ
Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.
Esegesi in lingua araba:
إِنَّ رَبَّكَ لَبِٱلۡمِرۡصَادِ
Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).
Esegesi in lingua araba:
فَأَمَّا ٱلۡإِنسَٰنُ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ رَبُّهُۥ فَأَكۡرَمَهُۥ وَنَعَّمَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَكۡرَمَنِ
Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti pọ́n mi lé.”
Esegesi in lingua araba:
وَأَمَّآ إِذَا مَا ٱبۡتَلَىٰهُ فَقَدَرَ عَلَيۡهِ رِزۡقَهُۥ فَيَقُولُ رَبِّيٓ أَهَٰنَنِ
Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: “Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi.”
Esegesi in lingua araba:
كَلَّاۖ بَل لَّا تُكۡرِمُونَ ٱلۡيَتِيمَ
Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.
Esegesi in lingua araba:
وَلَا تَحَٰٓضُّونَ عَلَىٰ طَعَامِ ٱلۡمِسۡكِينِ
Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.
Esegesi in lingua araba:
وَتَأۡكُلُونَ ٱلتُّرَاثَ أَكۡلٗا لَّمّٗا
Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.
Esegesi in lingua araba:
وَتُحِبُّونَ ٱلۡمَالَ حُبّٗا جَمّٗا
Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.
Esegesi in lingua araba:
كَلَّآۖ إِذَا دُكَّتِ ٱلۡأَرۡضُ دَكّٗا دَكّٗا
Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (tó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),
Esegesi in lingua araba:
وَجَآءَ رَبُّكَ وَٱلۡمَلَكُ صَفّٗا صَفّٗا
(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,
Esegesi in lingua araba:
 
Traduzione dei significati Sura: Al-Fajr
Indice delle Sure Numero di pagina
 
Traduzione dei Significati del Sacro Corano - Traduzione in yoruba - Abu Rahima Mikail - Indice Traduzioni

Tradotta dallo Sheikh Abu Rahima Mikail Aikoyini.

Chiudi