Bản dịch ý nghĩa nội dung Qur'an - Dịch thuật tiếng Yoruba * - Mục lục các bản dịch

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Ý nghĩa nội dung Câu: (34) Chương: Chương Luqman
إِنَّ ٱللَّهَ عِندَهُۥ عِلۡمُ ٱلسَّاعَةِ وَيُنَزِّلُ ٱلۡغَيۡثَ وَيَعۡلَمُ مَا فِي ٱلۡأَرۡحَامِۖ وَمَا تَدۡرِي نَفۡسٞ مَّاذَا تَكۡسِبُ غَدٗاۖ وَمَا تَدۡرِي نَفۡسُۢ بِأَيِّ أَرۡضٖ تَمُوتُۚ إِنَّ ٱللَّهَ عَلِيمٌ خَبِيرُۢ
Dájúdájú Allāhu, ọ̀dọ̀ Rẹ̀ ni ìmọ̀ Àkókò náà wà. Ó ń sọ òjò kalẹ̀. Ó mọ ohun tó wà nínú àpòlùkẹ́.¹ Ẹ̀mí kan kò sì mọ ohun tí ó máa ṣe níṣẹ́ ní ọ̀la. Ẹ̀mí kan kò sì mọ ilẹ̀ wo l’ó máa kú sí. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀, Alámọ̀tán.
1. “Ohun tó wà nínú àpòlùkẹ́”, ní abala ìrísí rẹ̀, ó lè di mímọ̀ fún ẹ̀dá nígbà tí ó bá ti di ọlẹ̀. Ìyẹn lè wáyé nípasẹ̀ yíya àwòrán ọlẹ̀ náà pẹ̀lú ẹ̀rọ ìyàwòrán-ọlẹ̀. Èyí kò sì lòdì sí àgbọ́yé āyah náà.
Àmọ́ “Ohun tó wà nínú àpòlùkẹ́”, ní abala kádàrá rẹ̀, bí ọ̀rọ̀ tayé àti tọ̀run ọlẹ̀ ṣe máa rí, kò sí ẹni tó nímọ̀ rẹ̀ lẹ́yìn Allāhu Olùmọ̀-jùlọ. Ìyẹn ni pé, kò sí ẹni tí ó nímọ̀ nípa kádàrá àtọ̀ tó wà nínú àpòlùkẹ́ àfi Allāhu. Èyí sì ni àgbọ́yé āyah náà.
Các Tafsir tiếng Ả-rập:
 
Ý nghĩa nội dung Câu: (34) Chương: Chương Luqman
Mục lục các chương Kinh Số trang
 
Bản dịch ý nghĩa nội dung Qur'an - Dịch thuật tiếng Yoruba - Mục lục các bản dịch

Bản dịch ý nghĩa nội dung Kinh Qur'an bằng tiếng Yoruba, dịch thuật bởi Sheikh Abu Rahimah Mika-il Ikweeni, xuất bản năm 1432 A.H

Đóng lại