《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 * - 译解目录

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

含义的翻译 段: (34) 章: 鲁格玛尼
إِنَّ ٱللَّهَ عِندَهُۥ عِلۡمُ ٱلسَّاعَةِ وَيُنَزِّلُ ٱلۡغَيۡثَ وَيَعۡلَمُ مَا فِي ٱلۡأَرۡحَامِۖ وَمَا تَدۡرِي نَفۡسٞ مَّاذَا تَكۡسِبُ غَدٗاۖ وَمَا تَدۡرِي نَفۡسُۢ بِأَيِّ أَرۡضٖ تَمُوتُۚ إِنَّ ٱللَّهَ عَلِيمٌ خَبِيرُۢ
Dájúdájú Allāhu, ọ̀dọ̀ Rẹ̀ ni ìmọ̀ Àkókò náà wà. Ó ń sọ òjò kalẹ̀. Ó mọ ohun tó wà nínú àpòlùkẹ́.¹ Ẹ̀mí kan kò sì mọ ohun tí ó máa ṣe níṣẹ́ ní ọ̀la. Ẹ̀mí kan kò sì mọ ilẹ̀ wo l’ó máa kú sí. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀, Alámọ̀tán.
1. “Ohun tó wà nínú àpòlùkẹ́”, ní abala ìrísí rẹ̀, ó lè di mímọ̀ fún ẹ̀dá nígbà tí ó bá ti di ọlẹ̀. Ìyẹn lè wáyé nípasẹ̀ yíya àwòrán ọlẹ̀ náà pẹ̀lú ẹ̀rọ ìyàwòrán-ọlẹ̀. Èyí kò sì lòdì sí àgbọ́yé āyah náà.
Àmọ́ “Ohun tó wà nínú àpòlùkẹ́”, ní abala kádàrá rẹ̀, bí ọ̀rọ̀ tayé àti tọ̀run ọlẹ̀ ṣe máa rí, kò sí ẹni tó nímọ̀ rẹ̀ lẹ́yìn Allāhu Olùmọ̀-jùlọ. Ìyẹn ni pé, kò sí ẹni tí ó nímọ̀ nípa kádàrá àtọ̀ tó wà nínú àpòlùkẹ́ àfi Allāhu. Èyí sì ni àgbọ́yé āyah náà.
阿拉伯语经注:
 
含义的翻译 段: (34) 章: 鲁格玛尼
章节目录 页码
 
《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 - 译解目录

古兰经泰卢固语译解,艾布·拉赫曼·米卡伊里·艾库比尼长老翻译,伊历1432年出版发行。

关闭