Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba * - Lexique des traductions

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

Traduction des sens Verset: (14) Sourate: AN-NISÂ’
وَمَن يَعۡصِ ٱللَّهَ وَرَسُولَهُۥ وَيَتَعَدَّ حُدُودَهُۥ يُدۡخِلۡهُ نَارًا خَٰلِدٗا فِيهَا وَلَهُۥ عَذَابٞ مُّهِينٞ
Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yapa (àṣẹ) Allāhu àti Òjíṣẹ́ Rẹ̀, tí ó sì ń tayọ àwọn ẹnu-ààlà tí Allāhu gbékalẹ̀, (Allāhu) yóò mú un wọ inú Iná kan. Olùṣegbére ni nínú rẹ̀. Ìyà tí í yẹpẹrẹ ẹ̀dá sì ń bẹ fún un.¹
1. Kíyè sí i, kò bá òfin ’Islām mu láti pín ogún ara ẹni sílẹ̀. Àti pé bí ènìyàn kò bá tí ì kú, dúkìá rẹ̀ kò ì di ogún fún ẹnì kan kan. Bákan náà, kí ẹnikẹ́ni má ṣe lérò pé tí òun bá ti ka àwọn āyah ogún pípín, òun ti nímọ̀ nípa ogún pípín nìyẹn. Rárá o. Ènìyàn gbọ́dọ̀ ka àwọn tírà tí àwọn onímọ̀ ẹ̀sìn ’Islām fi ṣàlàyé nípa ogún pípín. Fómúlà nìkan ni àwọn āyah ogún pípín jẹ́, bí a ṣe máa lo àwọn fọ́múlà náà wà nínú àwọn tírà ogún pípín.
Les exégèses en arabe:
 
Traduction des sens Verset: (14) Sourate: AN-NISÂ’
Lexique des sourates Numéro de la page
 
Traduction des sens du Noble Coran - Traduction en yorouba - Lexique des traductions

Traduction des sens du Noble Coran en langue yorouba par Cheikh Abû Rahimah Mikhaïl Aikweiny et publiée en l'an 1432 de l'Hégire.

Fermeture