《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 * - 译解目录

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

含义的翻译 章: 给亚迈   段:

Suuratul-Qiyaamah

لَآ أُقۡسِمُ بِيَوۡمِ ٱلۡقِيَٰمَةِ
Èmi (Allāhu) ń fi Ọjọ́ Àjíǹde búra.
阿拉伯语经注:
وَلَآ أُقۡسِمُ بِٱلنَّفۡسِ ٱللَّوَّامَةِ
Mo tún ń fi ẹ̀mí tó máa dá ara rẹ̀ ní ẹ̀bi búra.
阿拉伯语经注:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَلَّن نَّجۡمَعَ عِظَامَهُۥ
Ṣé ènìyàn lérò pé A kò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
阿拉伯语经注:
بَلَىٰ قَٰدِرِينَ عَلَىٰٓ أَن نُّسَوِّيَ بَنَانَهُۥ
Rárá. (À ń jẹ́) Alágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.
1.Àwọn ọmọníka ọwọ́ àti ọmọníka ẹsẹ̀, ọ̀tún rẹ̀ àti òsì rẹ̀. Ẹ tún wo sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:60-61 àti sūrah al-Mọ̄‘rij; 70:40-41.
阿拉伯语经注:
بَلۡ يُرِيدُ ٱلۡإِنسَٰنُ لِيَفۡجُرَ أَمَامَهُۥ
Rárá ènìyàn fẹ́ máa ṣe aburú lọ bẹ́ẹ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀
阿拉伯语经注:
يَسۡـَٔلُ أَيَّانَ يَوۡمُ ٱلۡقِيَٰمَةِ
ni ó fi ń bèèrè pé: “Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?”
阿拉伯语经注:
فَإِذَا بَرِقَ ٱلۡبَصَرُ
Nígbà tí ojú bá rí ìdààmú tó sì yà sílẹ̀ tí kò lè padé,
阿拉伯语经注:
وَخَسَفَ ٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
阿拉伯语经注:
وَجُمِعَ ٱلشَّمۡسُ وَٱلۡقَمَرُ
àti (nígbà) tí wọ́n bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn tí ìmọ́lẹ̀ méjèèjì pòóró,
阿拉伯语经注:
يَقُولُ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذٍ أَيۡنَ ٱلۡمَفَرُّ
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: “Níbo ni ibùsásí wà?”
阿拉伯语经注:
كَلَّا لَا وَزَرَ
Rárá, kò sí ibùsásí.
阿拉伯语经注:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمُسۡتَقَرُّ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
阿拉伯语经注:
يُنَبَّؤُاْ ٱلۡإِنسَٰنُ يَوۡمَئِذِۭ بِمَا قَدَّمَ وَأَخَّرَ
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun tó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
阿拉伯语经注:
بَلِ ٱلۡإِنسَٰنُ عَلَىٰ نَفۡسِهِۦ بَصِيرَةٞ
Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,
阿拉伯语经注:
وَلَوۡ أَلۡقَىٰ مَعَاذِيرَهُۥ
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
阿拉伯语经注:
لَا تُحَرِّكۡ بِهِۦ لِسَانَكَ لِتَعۡجَلَ بِهِۦٓ
Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.
阿拉伯语经注:
إِنَّ عَلَيۡنَا جَمۡعَهُۥ وَقُرۡءَانَهُۥ
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
阿拉伯语经注:
فَإِذَا قَرَأۡنَٰهُ فَٱتَّبِعۡ قُرۡءَانَهُۥ
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ إِنَّ عَلَيۡنَا بَيَانَهُۥ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
阿拉伯语经注:
كَلَّا بَلۡ تُحِبُّونَ ٱلۡعَاجِلَةَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, bí kò ṣe pé, ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé ni.
阿拉伯语经注:
وَتَذَرُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Ẹ sì ń gbé ọ̀run jù sílẹ̀.
阿拉伯语经注:
وُجُوهٞ يَوۡمَئِذٖ نَّاضِرَةٌ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
阿拉伯语经注:
إِلَىٰ رَبِّهَا نَاظِرَةٞ
Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.
阿拉伯语经注:
وَوُجُوهٞ يَوۡمَئِذِۭ بَاسِرَةٞ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
阿拉伯语经注:
تَظُنُّ أَن يُفۡعَلَ بِهَا فَاقِرَةٞ
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé wọ́n máa fi aburú kan òhun.
阿拉伯语经注:
كَلَّآ إِذَا بَلَغَتِ ٱلتَّرَاقِيَ
Kò rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
阿拉伯语经注:
وَقِيلَ مَنۡۜ رَاقٖ
A sì máa sọ pé: “Ǹjẹ́ olùpọfọ̀ kan wà bí (tí ó máa pọfọ̀ láti gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
阿拉伯语经注:
وَظَنَّ أَنَّهُ ٱلۡفِرَاقُ
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
阿拉伯语经注:
وَٱلۡتَفَّتِ ٱلسَّاقُ بِٱلسَّاقِ
Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.
阿拉伯语经注:
إِلَىٰ رَبِّكَ يَوۡمَئِذٍ ٱلۡمَسَاقُ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
阿拉伯语经注:
فَلَا صَدَّقَ وَلَا صَلَّىٰ
Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.
阿拉伯语经注:
وَلَٰكِن كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰ
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo ní irọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ ذَهَبَ إِلَىٰٓ أَهۡلِهِۦ يَتَمَطَّىٰٓ
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
阿拉伯语经注:
أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰ
(Ìparun nílé ayé) ló tọ́ sí ọ jùlọ (lórí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ wọ̀nyẹn). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ أَوۡلَىٰ لَكَ فَأَوۡلَىٰٓ
Lẹ́yìn náà, (Iná) ló tọ́ sí ọ jùlọ (ní ọ̀run). (Ìyẹn) ló sì tọ́ sí ọ jùlọ.
阿拉伯语经注:
أَيَحۡسَبُ ٱلۡإِنسَٰنُ أَن يُتۡرَكَ سُدًى
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
阿拉伯语经注:
أَلَمۡ يَكُ نُطۡفَةٗ مِّن مَّنِيّٖ يُمۡنَىٰ
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
阿拉伯语经注:
ثُمَّ كَانَ عَلَقَةٗ فَخَلَقَ فَسَوَّىٰ
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é tó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
阿拉伯语经注:
فَجَعَلَ مِنۡهُ ٱلزَّوۡجَيۡنِ ٱلذَّكَرَ وَٱلۡأُنثَىٰٓ
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti ara rẹ̀, akọ àti abo.
阿拉伯语经注:
أَلَيۡسَ ذَٰلِكَ بِقَٰدِرٍ عَلَىٰٓ أَن يُحۡـِۧيَ ٱلۡمَوۡتَىٰ
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
阿拉伯语经注:
 
含义的翻译 章: 给亚迈
章节目录 页码
 
《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 - 译解目录

古兰经泰卢固语译解,艾布·拉赫曼·米卡伊里·艾库比尼长老翻译,伊历1432年出版发行。

关闭