《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 * - 译解目录

PDF XML CSV Excel API
Please review the Terms and Policies

含义的翻译 章: 穆丹斯拉   段:

Suuratul-Muddathir

يَٰٓأَيُّهَا ٱلۡمُدَّثِّرُ
Ìwọ olùdaṣọbora.
阿拉伯语经注:
قُمۡ فَأَنذِرۡ
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
阿拉伯语经注:
وَرَبَّكَ فَكَبِّرۡ
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
阿拉伯语经注:
وَثِيَابَكَ فَطَهِّرۡ
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
阿拉伯语经注:
وَٱلرُّجۡزَ فَٱهۡجُرۡ
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
阿拉伯语经注:
وَلَا تَمۡنُن تَسۡتَكۡثِرُ
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
阿拉伯语经注:
وَلِرَبِّكَ فَٱصۡبِرۡ
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
阿拉伯语经注:
فَإِذَا نُقِرَ فِي ٱلنَّاقُورِ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
阿拉伯语经注:
فَذَٰلِكَ يَوۡمَئِذٖ يَوۡمٌ عَسِيرٌ
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
阿拉伯语经注:
عَلَى ٱلۡكَٰفِرِينَ غَيۡرُ يَسِيرٖ
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
阿拉伯语经注:
ذَرۡنِي وَمَنۡ خَلَقۡتُ وَحِيدٗا
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan (ìyẹn nínú ikùn ìyá rẹ̀).
阿拉伯语经注:
وَجَعَلۡتُ لَهُۥ مَالٗا مَّمۡدُودٗا
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
阿拉伯语经注:
وَبَنِينَ شُهُودٗا
àti àwọn ọmọkúnrin tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
阿拉伯语经注:
وَمَهَّدتُّ لَهُۥ تَمۡهِيدٗا
Mo sì fi àyè ìrọ̀rùn gbá a dáadáa.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ يَطۡمَعُ أَنۡ أَزِيدَ
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
阿拉伯语经注:
كَلَّآۖ إِنَّهُۥ كَانَ لِأٓيَٰتِنَا عَنِيدٗا
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
阿拉伯语经注:
سَأُرۡهِقُهُۥ صَعُودًا
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná)¹.
[1] Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
阿拉伯语经注:
إِنَّهُۥ فَكَّرَ وَقَدَّرَ
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
阿拉伯语经注:
فَقُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ قُتِلَ كَيۡفَ قَدَّرَ
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ نَظَرَ
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ عَبَسَ وَبَسَرَ
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
阿拉伯语经注:
ثُمَّ أَدۡبَرَ وَٱسۡتَكۡبَرَ
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìndà, ó sì ṣègbéraga.
阿拉伯语经注:
فَقَالَ إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا سِحۡرٞ يُؤۡثَرُ
Ó sì wí pé: “Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
阿拉伯语经注:
إِنۡ هَٰذَآ إِلَّا قَوۡلُ ٱلۡبَشَرِ
Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara”
阿拉伯语经注:
سَأُصۡلِيهِ سَقَرَ
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
阿拉伯语经注:
وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا سَقَرُ
Kí l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ iná Saƙọr?
阿拉伯语经注:
لَا تُبۡقِي وَلَا تَذَرُ
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.¹
1. Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
阿拉伯语经注:
لَوَّاحَةٞ لِّلۡبَشَرِ
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
阿拉伯语经注:
عَلَيۡهَا تِسۡعَةَ عَشَرَ
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
阿拉伯语经注:
وَمَا جَعَلۡنَآ أَصۡحَٰبَ ٱلنَّارِ إِلَّا مَلَٰٓئِكَةٗۖ وَمَا جَعَلۡنَا عِدَّتَهُمۡ إِلَّا فِتۡنَةٗ لِّلَّذِينَ كَفَرُواْ لِيَسۡتَيۡقِنَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَيَزۡدَادَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُوٓاْ إِيمَٰنٗا وَلَا يَرۡتَابَ ٱلَّذِينَ أُوتُواْ ٱلۡكِتَٰبَ وَٱلۡمُؤۡمِنُونَ وَلِيَقُولَ ٱلَّذِينَ فِي قُلُوبِهِم مَّرَضٞ وَٱلۡكَٰفِرُونَ مَاذَآ أَرَادَ ٱللَّهُ بِهَٰذَا مَثَلٗاۚ كَذَٰلِكَ يُضِلُّ ٱللَّهُ مَن يَشَآءُ وَيَهۡدِي مَن يَشَآءُۚ وَمَا يَعۡلَمُ جُنُودَ رَبِّكَ إِلَّا هُوَۚ وَمَا هِيَ إِلَّا ذِكۡرَىٰ لِلۡبَشَرِ
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn tó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: “Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?” Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
阿拉伯语经注:
كَلَّا وَٱلۡقَمَرِ
Ẹ gbọ́! Allāhu fi òṣùpá búra.
阿拉伯语经注:
وَٱلَّيۡلِ إِذۡ أَدۡبَرَ
Ó tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.
阿拉伯语经注:
وَٱلصُّبۡحِ إِذَآ أَسۡفَرَ
Ó tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́ búra.
阿拉伯语经注:
إِنَّهَا لَإِحۡدَى ٱلۡكُبَرِ
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) tó tóbi.
阿拉伯语经注:
نَذِيرٗا لِّلۡبَشَرِ
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
阿拉伯语经注:
لِمَن شَآءَ مِنكُمۡ أَن يَتَقَدَّمَ أَوۡ يَتَأَخَّرَ
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn (nínú ẹ̀ṣẹ̀).
阿拉伯语经注:
كُلُّ نَفۡسِۭ بِمَا كَسَبَتۡ رَهِينَةٌ
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun tó ṣe níṣẹ́.
阿拉伯语经注:
إِلَّآ أَصۡحَٰبَ ٱلۡيَمِينِ
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
阿拉伯语经注:
فِي جَنَّٰتٖ يَتَسَآءَلُونَ
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
阿拉伯语经注:
عَنِ ٱلۡمُجۡرِمِينَ
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
阿拉伯语经注:
مَا سَلَكَكُمۡ فِي سَقَرَ
“Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?”
阿拉伯语经注:
قَالُواْ لَمۡ نَكُ مِنَ ٱلۡمُصَلِّينَ
Wọn yóò wí pé: “Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
阿拉伯语经注:
وَلَمۡ نَكُ نُطۡعِمُ ٱلۡمِسۡكِينَ
Àwa kò sì sí nínú àwọn tó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
阿拉伯语经注:
وَكُنَّا نَخُوضُ مَعَ ٱلۡخَآئِضِينَ
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
阿拉伯语经注:
وَكُنَّا نُكَذِّبُ بِيَوۡمِ ٱلدِّينِ
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́
阿拉伯语经注:
حَتَّىٰٓ أَتَىٰنَا ٱلۡيَقِينُ
títí ikú fi dé bá wa.”
阿拉伯语经注:
فَمَا تَنفَعُهُمۡ شَفَٰعَةُ ٱلشَّٰفِعِينَ
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
阿拉伯语经注:
فَمَا لَهُمۡ عَنِ ٱلتَّذۡكِرَةِ مُعۡرِضِينَ
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
阿拉伯语经注:
كَأَنَّهُمۡ حُمُرٞ مُّسۡتَنفِرَةٞ
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tó ń sá lọ,
阿拉伯语经注:
فَرَّتۡ مِن قَسۡوَرَةِۭ
tó sá fún kìnìhún?
阿拉伯语经注:
بَلۡ يُرِيدُ كُلُّ ٱمۡرِيٕٖ مِّنۡهُمۡ أَن يُؤۡتَىٰ صُحُفٗا مُّنَشَّرَةٗ
Rárá, ńṣe ni ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
阿拉伯语经注:
كَلَّاۖ بَل لَّا يَخَافُونَ ٱلۡأٓخِرَةَ
Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.
阿拉伯语经注:
كَلَّآ إِنَّهُۥ تَذۡكِرَةٞ
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
阿拉伯语经注:
فَمَن شَآءَ ذَكَرَهُۥ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́, kí ó rántí rẹ̀.
阿拉伯语经注:
وَمَا يَذۡكُرُونَ إِلَّآ أَن يَشَآءَ ٱللَّهُۚ هُوَ أَهۡلُ ٱلتَّقۡوَىٰ وَأَهۡلُ ٱلۡمَغۡفِرَةِ
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì ni àforíjìn.
阿拉伯语经注:
 
含义的翻译 章: 穆丹斯拉
章节目录 页码
 
《古兰经》译解 - 约鲁巴语翻译。 - 译解目录

古兰经泰卢固语译解,艾布·拉赫曼·米卡伊里·艾库比尼长老翻译,伊历1432年出版发行。

关闭